Nehemiah 9 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 9:1-38

Àwọn ọkùnrin Israẹli jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn

1Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn. 2Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn. 3Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn. 4Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn 5Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé: “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.”

“Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ. 6Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.

7“Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu. 8Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.

9“Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun pupa. 10Ìwọ rán iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí. 11Ìwọ pín Òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá. 12Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.

13“Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára. 14Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ. 15Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.

16“Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ. 17Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀, 18Nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.

19“Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn. 20Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ. 21Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.

22“Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani. 23Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀ 24Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n. 25Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ

26“Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì. 27Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.

28“Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.

29“Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́. 30Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́. 31Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.

32“Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní. 33Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú. 34Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn. 35Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.

36“Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde. 37Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.

Àdéhùn àwọn ènìyàn

38“Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”

Persian Contemporary Bible

نحميا 9:1‏-38

1‏-2در روز بيست و چهارم همان ماه، بنی‌اسرائيل جمع شدند تا روزه بگيرند. آنها لباس عزا بر تن داشتند و بر سر خود خاک ريخته بودند. بنی‌اسرائيل كه خود را از تمام بيگانگان جدا كرده بودند ايستادند و به گناهان خود و اجدادشان اعتراف نمودند. 3حدود سه ساعت از تورات خداوند، خدايشان با صدای بلند برای ايشان خوانده شد و سه ساعت ديگر به گناهان خود اعتراف كردند و همه خداوند، خدای خود را پرستش نمودند. 4سپس يک دسته از لاويان به نامهای يشوع، بانی، قدمی‌ئيل، شبنيا، بونی، شربيا، بانی و كنانی روی سكو ايستادند و با صدای بلند نزد خداوند، خدای خود دعا كردند.

5آنگاه يشوع، قدمی‌ئيل، بانی، حشبنيا، شربيا، هوديا، شبنيا و فتحيا كه همگی از لاويان بودند با اين كلمات قوم را در دعا هدايت كردند: «برخيزيد و خداوند، خدای خود را كه از ازل تا ابد باقی است، ستايش كنيد!

«سپاس بر نام پرجلال تو كه بالاتر از تمام تمجيدهای ماست! 6تو تنها خداوند هستی. آسمانها و ستارگان را تو آفريدی؛ زمين و دريا و موجودات آنها را تو به وجود آوردی؛ تو به همهٔ اينها حيات بخشيدی. تمام فرشتگان آسمان، تو را سجده می‌كنند.

7«ای خداوند، تو همان خدايی هستی كه ابرام را انتخاب كردی، او را از شهر اور كلدانیان بيرون آوردی و نام او را به ابراهيم تبديل نمودی. 8او نسبت به تو امين بود و تو با او عهد بستی و به او وعده دادی كه سرزمين كنعانی‌ها، حيتی‌ها، اموری‌ها، فرزی‌ها، يبوسی‌ها و جرجاشی‌ها را به او و به فرزندان او ببخشی. تو به قول خود عمل كردی، زيرا امين هستی.

9«تو رنج و سختی اجداد ما را در مصر ديدی و آه و نالهٔ آنها را در كنار دريای سرخ شنيدی. 10معجزات بزرگی به فرعون و سرداران و قوم او نشان دادی، چون می‌ديدی چگونه مصریان بر اجداد ما ظلم می‌كنند. به سبب اين معجزات، شهرت يافتی و شهرتت تا به امروز باقی است. 11دريا را شكافتی و از ميان آب، راهی برای عبور قوم خود آماده ساختی و دشمنانی را كه آنها را تعقيب می‌كردند به دريا انداختی و آنها مثل سنگ به ته دريا رفتند و غرق شدند. 12در روز، با ستون ابر و در شب با ستون آتش، اجداد ما را در راهی كه می‌بايست می‌رفتند هدايت كردی.

13«تو بر كوه سينا نزول فرمودی و از آسمان با ايشان سخن گفتی و قوانين خوب و احكام راست به ايشان بخشيدی. 14توسط موسی شريعت را به آنان دادی و روز مقدس سبت را عطا كردی. 15وقتی گرسنه شدند، از آسمان به ايشان نان دادی، وقتی تشنه بودند، از صخره به ايشان آب دادی. به آنها گفتی به سرزمينی كه قسم خورده بودی به ايشان بدهی داخل شوند و آن را به تصرف خود در بياورند. 16ولی اجداد ما متكبر و خودسر بودند و نخواستند از دستورات تو اطاعت كنند. 17آنها نه فقط به دستورات تو گوش ندادند و معجزاتی را كه برای ايشان كرده بودی فراموش نمودند، بلكه ياغی شدند و رهبری برای خود انتخاب كردند تا دوباره به مصر، سرزمين بردگی برگردند. ولی تو خدائی بخشنده و رحيم و مهربان هستی؛ تو پر از محبت هستی و دير خشمگين می‌شوی؛ به همين جهت ايشان را ترک نكردی. 18با اينكه به تو اهانت نموده مجسمهٔ گوساله‌ای را ساختند و گفتند: ”اين خدای ماست كه ما را از مصر بيرون آورد.“ ايشان به طرق مختلف گناه كردند. 19ولی تو به سبب رحمت عظيم خود ايشان را در بيابان ترک نكردی و ستون ابر را كه هر روز ايشان را هدايت می‌كرد و نيز ستون آتش را كه هر شب راه را به ايشان نشان می‌داد، از ايشان دور نساختی. 20روح مهربان خود را فرستادی تا ايشان را تعليم دهد. برای رفع گرسنگی، نان آسمانی را به آنها دادی و برای رفع تشنگی، آب به ايشان بخشيدی. 21چهل سال در بيابان از ايشان نگهداری كردی به طوری كه هرگز به چيزی محتاج نشدند؛ نه لباسشان پاره شد و نه پاهای ايشان ورم كرد.

22«ايشان را كمک كردی تا قومها را شكست دهند و سرزمينهاشان را تصرف كرده، مرزهای خود را وسيع سازند. ايشان سرزمين حشبون را از سيحون پادشاه و سرزمين باشان را از عوج پادشاه گرفتند. 23جمعيت ايشان را به اندازهٔ ستارگان آسمان زياد كردی و آنها را به سرزمينی آوردی كه به اجدادشان وعده داده بودی. 24آنها به سرزمين كنعان داخل شدند و تو اهالی آنجا را مغلوب ايشان ساختی تا هر طور كه بخواهند با پادشاهان و مردم آنجا رفتار كنند. 25قوم تو شهرهای حصاردار و زمينهای حاصلخيز را گرفتند، خانه‌هايی را كه پر از چيزهای خوب بود از آن خود ساختند، و چاههای آب و باغهای انگور و زيتون و درختان ميوه را تصرف كردند. آنها خوردند و سير شدند و از نعمتهای بی‌حد تو برخوردار گشتند.

26«ولی ايشان نافرمانی كردند و نسبت به تو ياغی شدند. به دستورات تو توجه نكردند و انبيای تو را كه سعی داشتند ايشان را به سوی تو بازگردانند، كشتند و با اين كارها به تو اهانت نمودند. 27پس تو نيز آنها را در چنگ دشمن اسير كردی تا بر ايشان ظلم كنند. اما وقتی از ظلم دشمن نزد تو ناله كردند، تو از آسمان، دعای ايشان را شنيدی و به سبب رحمت عظيم خود رهبرانی فرستادی تا ايشان را از چنگ دشمن نجات دهند. 28ولی وقتی از امنيت برخوردار شدند باز گناه كردند. آنگاه تو به دشمن اجازه دادی بر ايشان مسلط شود. با اين حال، وقتی قومت به سوی تو بازگشتند و كمک خواستند، از آسمان به نالهٔ ايشان گوش دادی و با رحمت عظيم خود ايشان را بارها نجات بخشيدی. 29به ايشان هشدار دادی تا دستورات تو را اطاعت كنند، ولی به جای اطاعت از احكام حيات‌بخش تو، با تكبر و سرسختی از تو رو برگردانيدند و احكام تو را زير پا گذاشتند. 30سالها با ايشان مدارا كردی و بوسيلهٔ روح خود توسط انبیا به ايشان هشدار دادی، ولی ايشان توجه نكردند. پس باز اجازه دادی قومهای ديگر بر ايشان مسلط شوند. 31ولی باز به سبب رحمت عظيم خود، ايشان را به کلی از بين نبردی و ترک نگفتی، زيرا تو خدايی رحيم و مهربان هستی!

32«و حال ای خدای ما، ای خدای عظيم و قادر و مهيب كه به وعده‌های پر از رحمت خود وفا می‌كنی، اين همه رنج و سختی كه كشيده‌ايم در نظر تو ناچيز نيايد. از زمانی كه پادشاهان آشور بر ما پيروز شدند تا امروز، بلاهای زيادی بر ما و پادشاهان و بزرگان و كاهنان و انبیا و اجداد ما نازل شده است. 33تو عادل هستی و هر بار كه ما را مجازات كرده‌ای به حق بوده است، زيرا ما گناه كرده‌ايم. 34پادشاهان، سران قوم، كاهنان و اجداد ما دستورات تو را اطاعت نكردند و به اخطارهای تو گوش ندادند. 35در سرزمين پهناور و حاصلخيزی كه به ايشان دادی از نعمتهای فراوان تو برخوردار شدند، ولی تو را عبادت نكردند و از اعمال زشت خود دست برنداشتند.

36«اما اينک در اين سرزمين حاصلخيز كه به اجدادمان دادی تا از آن برخوردار شويم، برده‌ای بيش نيستيم. 37محصول اين زمين نصيب پادشاهانی می‌شود كه تو به سبب گناهانمان آنها را بر ما مسلط كرده‌ای. آنها هر طور می‌خواهند بر جان و مال ما حكومت می‌كنند و ما در شدت سختی گرفتار هستيم. 38با توجه به اين اوضاع، اينک ای خداوند ما با تو پيمان ناگسستنی می‌بنديم تا تو را خدمت كنيم؛ و سران قوم ما همراه لاويان و كاهنان اين پيمان را مهر می‌كنند.»