Nehemiah 9 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 9:1-38

Àwọn ọkùnrin Israẹli jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn

1Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn. 2Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn. 3Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn. 4Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn 5Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé: “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.”

“Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ. 6Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.

7“Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu. 8Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.

9“Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun pupa. 10Ìwọ rán iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí. 11Ìwọ pín Òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá. 12Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.

13“Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára. 14Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ. 15Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.

16“Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ. 17Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀, 18Nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.

19“Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn. 20Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ. 21Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.

22“Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani. 23Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀ 24Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n. 25Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ

26“Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì. 27Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.

28“Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.

29“Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́. 30Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́. 31Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.

32“Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní. 33Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú. 34Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn. 35Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.

36“Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde. 37Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.

Àdéhùn àwọn ènìyàn

38“Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”

La Bible du Semeur

Néhémie 9:1-37

Le peuple confesse ses péchés

1Le vingt-quatrième jour du même mois9.1 31 octobre 445 av. J.-C., les Israélites, revêtus d’habits de toile de sac et la tête couverte de poussière, s’assemblèrent pour un temps de jeûne. 2Ceux qui étaient Israélites de souche s’étaient séparés de tous les gens d’origine étrangère9.2 La réunion eut lieu dans le parvis du Temple où seuls les Juifs avaient accès. ; puis ils se présentèrent pour confesser leurs péchés et ceux de leurs ancêtres. 3Ils se mirent debout, chacun à sa place, et on lut pendant trois heures dans le livre de la Loi de l’Eternel, leur Dieu. Puis, pendant trois autres heures, ils se tinrent prosternés devant l’Eternel, leur Dieu, et confessèrent leurs péchés.

4Josué, Bani, Qadmiel, Shebania, Bounni, Shérébia, Bani et Kenani montèrent sur l’estrade dressée pour les lévites et implorèrent l’Eternel, leur Dieu, à haute voix. 5Puis les lévites, Josué, Qadmiel, Bani, Hashabnia, Shérébia, Hodiya, Shebania et Petahya s’écrièrent :

Levez-vous, bénissez l’Eternel, votre Dieu, pour toute l’éternité. Oui, que l’on te bénisse, toi dont la gloire surpasse tout ce que la louange peut exprimer ! 6C’est toi, Eternel, toi qui es l’unique ! Tu as fait le ciel, les cieux les plus élevés et tous les astres qui s’y trouvent ! Tu as créé la terre et tout ce qui est dessus, les mers et tout ce qu’elles renferment. Tu donnes la vie à tous les êtres, et l’armée céleste se prosterne devant toi.

7C’est toi, Eternel Dieu, qui as choisi Abram. Tu l’as fait quitter Our des Chaldéens et tu lui as donné le nom d’Abraham9.7 Voir Gn 12.1 ; 17.5.. 8Tu as constaté que son cœur t’était fidèle, et tu as conclu une alliance avec lui en lui promettant de donner à sa descendance le pays des Cananéens, des Hittites, des Amoréens, des Phéréziens, des Yebousiens et des Guirgasiens9.8 Voir Gn 15.18-21.. Et tu as accompli tes promesses, car tu es juste.

9Tu as vu la misère de nos ancêtres en Egypte, et tu as entendu lorsqu’ils ont imploré ton aide sur les bords de la mer des Roseaux9.9 Voir Ex 3.7 ; 14.10-12.. 10Tu as accompli des signes extraordinaires et des prodiges contre le pharaon, contre tous ses ministres et contre tout le peuple de son pays, parce que tu savais avec quelle cruauté les Egyptiens avaient traité nos ancêtres. Ainsi tu t’es acquis une grande renommée qui s’est maintenue jusqu’à ce jour9.10 Voir Ex 7 à 12.. 11Tu as ouvert la mer devant eux, et nos ancêtres l’ont traversée à sec : mais tu as précipité ceux qui les poursuivaient dans les flots comme une pierre qui s’enfonce dans des eaux tumultueuses9.11 Voir Ex 14.21-29 ; 15.4-5..

12Tu as conduit ton peuple, le jour par une colonne de nuée, et la nuit par une colonne de feu qui leur éclairait le chemin qu’ils devaient suivre9.12 Voir Ex 13.21-22.. 13Tu es descendu sur le mont Sinaï, tu leur as parlé du haut du ciel et tu leur as communiqué des articles de droit justes, des lois vraies, des ordonnances et des commandements excellents9.13 Pour les v. 13-14, voir Ex 19 à 23.. 14Tu leur as fait connaître ton saint sabbat et tu leur as donné, par l’intermédiaire de ton serviteur Moïse, des commandements, des ordonnances et une Loi. 15Tu leur as fourni du ciel du pain pour apaiser leur faim, et tu as fait jaillir de l’eau du rocher pour étancher leur soif. Tu leur as commandé d’aller prendre possession du pays que tu avais promis par serment de leur donner9.15 Voir Ex 16.4-15 ; 17.1-7 ; Dt 1.21..

16Mais eux et nos ancêtres sont devenus orgueilleux et se sont montrés rebelles. Ils n’ont pas obéi à tes commandements ; 17oui, ils ont refusé d’obéir, oubliant les œuvres extraordinaires que tu avais accomplies pour eux. Ils se sont rebellés et, dans leur révolte, ils ont voulu se donner un chef pour retourner à leur esclavage9.17 Nb 14.4 (voir Ps 106).. Mais toi, tu es un Dieu qui pardonne, un Dieu compatissant et qui fait grâce, tu es lent à te mettre en colère et d’une immense bonté : tu ne les as pas abandonnés9.17 Voir Ex 34.6 ; Nb 14.18., 18même quand ils se sont fabriqué un veau en métal fondu en déclarant : « Voici ton Dieu qui t’a fait sortir d’Egypte ! » et qu’ils ont proféré contre toi de graves blasphèmes9.18 Voir Ex 32.1-4.. 19Dans ton immense compassion, tu ne les as pas abandonnés au désert, et la colonne de nuée ne s’est pas écartée d’eux, elle a continué à les guider le jour sur leur chemin, et pendant la nuit, la colonne de feu n’a pas cessé d’éclairer pour eux la route qu’ils avaient à suivre9.19 Pour les v. 19-21, voir Dt 8.2-4.. 20Tu leur as donné ton bon Esprit pour leur accorder du discernement. Tu ne leur as pas refusé la manne dont tu les nourrissais et tu as continué à leur donner de l’eau pour étancher leur soif.

21Pendant quarante ans, tu as pourvu à leurs besoins dans le désert, et ils n’ont manqué de rien, leurs vêtements ne se sont pas usés et leurs pieds ne se sont pas enflés. 22Tu leur as permis de conquérir des royaumes et des peuples, et tu leur as donné en partage les territoires de ceux-ci jusqu’à leurs frontières. Ils ont pris possession du pays de Sihôn, roi de Heshbôn et de celui d’Og, roi du Basan9.22 Voir Nb 21.21-35.. 23Tu leur as accordé une descendance aussi nombreuse que les étoiles du ciel9.23 Voir Gn 15.5 ; 22.17 ; Dt 1.10. et tu les as conduits dans ce pays que tu avais ordonné à leurs ancêtres d’aller conquérir9.23 Voir Dt 10.11 ; 31.7.. 24Leurs descendants y sont entrés et en ont pris possession. Tu as soumis devant eux les Cananéens qui habitaient le pays, tu les as livrés en leur pouvoir, avec les rois et les peuples de cette région, pour qu’ils les traitent comme ils le voulaient9.24 Voir Jos 11.23.. 25Ils se sont emparés de villes fortifiées et de terres fertiles. Ils ont pris possession de maisons regorgeant de biens, de citernes déjà creusées, de vignes, d’oliviers, d’arbres fruitiers à profusion. Par ta grande bonté, ils ont mangé à leur faim et avec abondance, et ils ont vécu dans les délices9.25 Voir Dt 6.10-11..

26Mais voici qu’ils ont été indociles et se sont révoltés contre toi, ils ont tourné le dos à ta Loi, ils ont tué tes prophètes qui les enjoignaient de revenir à toi, et ils se sont rendus coupables de graves blasphèmes9.26 Pour les v. 26-28, voir Jg 2.6 à 3.6.. 27Alors tu les as livrés au pouvoir de leurs ennemis qui les ont attaqués. Mais une fois dans la détresse, ils ont imploré ton secours ; et toi, tu les as entendus du haut du ciel et, dans ton immense compassion, tu leur as envoyé des libérateurs qui les ont délivrés de leurs ennemis. 28Cependant, dès qu’ils avaient retrouvé la paix, les voilà qui recommençaient à faire le mal devant toi ! Alors tu les as de nouveau livrés au pouvoir de leurs ennemis, qui les ont opprimés. De nouveau, ils ont imploré ton secours ; et toi, tu les as entendus du haut du ciel et, dans ta grande compassion, tu les as délivrés maintes et maintes fois.

29Tu leur as enjoint de revenir à ta Loi ; mais eux, dans leur orgueil, ils ont refusé d’obéir à tes commandements. Ils ont transgressé tes lois qui, pourtant, font vivre ceux qui les appliquent. Ils se sont montrés rebelles, se sont obstinés dans leur révolte, et n’ont rien voulu entendre9.29 Voir Lv 18.5.. 30Tu les as supportés pendant de longues années et, inlassablement, ton Esprit les a avertis par l’intermédiaire de tes prophètes, mais ils n’ont pas écouté. Alors tu les as livrés à des peuples étrangers9.30 Voir 2 R 17.13-18 ; 2 Ch 36.15-16.. 31Mais même alors, dans ta grande compassion, tu ne les as pas complètement anéantis et tu ne les as pas abandonnés, car tu es un Dieu compatissant et qui fait grâce.

Les supplications du peuple

32Maintenant, ô notre Dieu, toi le Dieu grand, puissant et redoutable, qui es fidèle à ton alliance et qui nous conserves ta bonté, ne considère pas comme peu de chose toutes les grandes épreuves que nous avons rencontrées, nous, nos rois, nos dirigeants, nos prêtres, nos prophètes, nos ancêtres et tout ton peuple depuis l’époque de la domination assyrienne jusqu’à ce jour.

33Tu as été juste dans tout ce qui nous est arrivé, car tu as agi en toute fidélité, alors que nous, nous avons fait le mal. 34Nos rois, nos dirigeants, nos prêtres et nos ancêtres n’ont pas appliqué ta Loi et n’ont pas respecté tes commandements ; ils n’ont pas prêté attention aux avertissements que tu leur adressais. 35Tant qu’ils jouissaient dans leur royaume des nombreux bienfaits que tu leur accordais dans le pays spacieux et fertile que tu leur avais donné, ils ne t’ont pas adoré et ne se sont pas détournés de leurs mauvaises actions.

36A présent, nous voici esclaves ! Oui, nous sommes réduits à la servitude dans le pays que tu as donné à nos ancêtres pour qu’ils jouissent de ses fruits et de ses biens ! 37Les moissons abondantes qu’il produit profitent aux rois que tu nous as imposés à cause de nos fautes ; ils disposent à leur gré de notre corps et de nos troupeaux, et nous voilà plongés dans une profonde détresse.