Nehemiah 9 – YCB & APSD-CEB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 9:1-38

Àwọn ọkùnrin Israẹli jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn

1Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn. 2Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn. 3Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn. 4Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn 5Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé: “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.”

“Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ. 6Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.

7“Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu. 8Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.

9“Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun pupa. 10Ìwọ rán iṣẹ́ ààmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí. 11Ìwọ pín Òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá. 12Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.

13“Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára. 14Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ. 15Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.

16“Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ. 17Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀, 18Nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.

19“Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn. 20Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ. 21Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.

22“Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani. 23Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀ 24Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n. 25Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ

26“Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì. 27Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.

28“Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.

29“Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́. 30Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́. 31Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.

32“Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní. 33Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú. 34Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn. 35Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.

36“Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde. 37Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.

Àdéhùn àwọn ènìyàn

38“Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”

Ang Pulong Sa Dios

Nehemias 9:1-38

Naghinulsol ang mga Israelinhon sa Ilang mga sala

1Sa ika-24 nga adlaw sa mao gihapon nga bulan, nagtigom ang mga Israelinhon aron magpuasa. Nagbisti silag sako ug nagbutang ug abo sa ilang ulo sa pagpakita sa ilang pagsubo. 2Gilain nila ang ilang kaugalingon gikan sa mga dili Israelinhon. Nanindog sila ug gisulti nila ang ilang mga sala ug ang mga sala sa ilang mga katigulangan. 3Nagpabilin sila sa pagtindog sulod sa tulo ka oras samtang gibasa kanila ang Kasugoan sa Ginoo nga ilang Dios. Ug sulod sa laing tulo ka oras gisulti nila ang ilang mga sala ug nagsimba sa Ginoo nga ilang Dios. 4Ang mga Levita mitindog sa hagdanan ug nagaampo ug kusog sa Ginoo nga ilang Dios. Sila mao si Jeshua, Bani, Kadmiel, Shebania, Buni, Sherebia, ug Kenani. 5Unya ang mga Levita nga sila si Jeshua, Kadmiel, Bani, Hashabnea, Sherebia, Hodia, Shebania, ug Petahia miingon, “Tindog kamo ug dayega ang Ginoo nga inyong Dios sa walay kataposan!”9:5 sa walay kataposan: o, nga nagakinabuhi gikan kaniadto hangtod sa kahangtoran.

Unya miingon sila,O Ginoo, dalaygon ang imong pagkagamhanan! Dili kini matupngan sa among mga pagdayeg. 6Ikaw lang ang Ginoo. Gihimo mo ang langit, ang yuta, ang dagat, ug ang tanang anaa niini. Ginahatagan mo ug kinabuhi ang tanan mong binuhat, ug ginasimba ka sa mga anghel sa langit.

7“Ikaw ang Ginoong Dios nga nagpili kang Abram ug nagdala kaniya pagawas sa Ur, nga sakop sa pagdumala sa mga Kaldeanhon.9:7 Kaldeanhon: Mga katawhan nga nagpuyo kaniadto sa habagatang bahin sa Babilonia. Sa kadugayan nahimong Kaldeanhon ang tawag sa mga taga-Babilonia. Ug ginganlan mo siyag Abraham. 8Nakita mo nga matinumanon siya kanimo, ug naghimo ka ug kasabotan kaniya nga imong ihatag sa iyang mga kaliwat ang yuta sa mga Canaanhon, Hitihanon, Amorihanon, Perisihanon, Jebusihanon, ug sa mga Gergasihanon. Ug gituman mo ang imong saad kanila, tungod kay matarong ka.

9“Nakita mo ang pag-antos sa among mga katigulangan sa Ehipto. Nadungog mo ang pagpangayo nilag tabang kanimo didto sa Pulang Dagat. 10Naghimo ka ug mga milagro ug mga katingalahang butang batok sa Faraon, ug sa tanan niyang mga opisyal ug katawhan, kay nahibaloan mo kon giunsa nila pagdaog-daog ang among mga katigulangan. Ug ang imong ngalan bantogan hangtod karon. 11Gitunga mo ang dagat atubangan sa imong katawhan aron makaagi sila sa yuta nga mala. Ang ilang mga kaaway nga naggukod kanila gitambog mo sa kinahiladman sa dagat nga sama sa bato nga gitambog sa sulog nga tubig. 12Kon adlaw, gitultolan mo sila pinaagi sa panganod nga daw haligi, ug kon gabii, pinaagi sa kalayo nga daw haligi, aron sa paghatag ug kahayag sa dalan nga ilang gilakwan.

13“Nanaog ka sa Bukid sa Sinai gikan sa langit ug nakigsulti ka kanila. Gihatagan mo silag husto nga mga lagda ug mga patakaran ug maayo nga mga tulumanon ug mga sugo. 14Gitudloan mo sila bahin sa ilang himuon sa Adlaw nga Igpapahulay. Ug gisugo mo sila pinaagi sa imong alagad nga si Moises nga tumanon nila ang imong mga sugo, mga tulumanon, ug mga lagda. 15Sa dihang gigutom sila, gihatagan mo silag pagkaon gikan sa langit, ug sa dihang giuhaw sila, gipainom mo silag tubig gikan sa bato. Giingnan mo sila nga sudlon nila ug panag-iyahon ang yuta nga imong gisaad nga ihatag kanila. 16Apan sila nga among mga katigulangan mapahitas-on, gahig ulo, ug wala motuman sa imong mga sugo. 17Nagdumili sila sa pagpamati kanimo, ug gikalimtan nila ang mga milagro nga imong gihimo alang kanila. Nagmagahi sila, ug misupak kanimo pinaagi sa pagpili ug mga pangulo nga modala kanila pagbalik sa pagkaulipon sa Ehipto. Apan mapinasayloon ka nga Dios, maloloy-on, puno sa grasya, dili daling masuko, ug mahigugmaon. Busa wala mo sila isalikway 18bisan naghimo silag rebulto nga baka ug miingon, ‘Mao kini ang atong dios nga nagpagawas kanato gikan sa Ehipto.’ Labihan gayod ang ilang pagpasipala kanimo! 19Apan tungod sa imong dakong kalooy kanila, wala mo sila pasagdi sa disyerto. Wala mobiya kanila ang panganod nga daw haligi nga nagatultol kanila kon adlaw, ug ang kalayo nga daw haligi nga nagahatag ug kahayag sa dalan nga ilang ginalakwan kon gabii. 20Gihatag mo kanila ang imong maayong Espiritu sa pagtudlo kanila. Wala nimo sila hikawi sa pagkaon sa manna, ug padayon mo silang gihatagan ug tubig alang sa ilang kauhaw. 21Giatiman mo sila sulod sa 40 ka tuig didto sa kamingawan, busa wala gayod sila makulangi sa ilang mga kinahanglanon. Wala modaan ang ilang mga bisti ug wala usab maluthi ang ilang mga tiil sa paglakaw.

22“Gitugyan mo kanila ang mga gingharian, mga nasod, ug ang mga yuta sa ilang palibot. Giilog nila ang yuta sa Heshbon nga gidumalahan ni Haring Sihon, ug ang yuta sa Basan nga gidumalahan ni Haring Og. 23Gipadaghan mo ang ilang mga kaliwat, sama sa mga bitoon sa langit. Gidala mo sila sa yuta nga imong gisaad sa ilang mga katigulangan nga ilang sudlon ug panag-iyahan. 24Busa gisulod nila kini ug gisakop. Gipapildi mo kanila ang mga Canaanhon nga nagpuyo niadtong yutaa. Gitugyan mo kanila ang mga Canaanhon apil ang ilang mga hari aron himuon nila ang gusto nilang himuon sa mga Canaanhon. 25Giilog sa imong katawhan ang pinarilan nga mga lungsod ug ang mabungahong mga yuta. Giilog usab nila ang mga balay nga puno sa maayong mga butang, mga atabay, mga ubasan, mga tamnanan sa olibo, ug ang mga punoan sa kahoy nga labihan kadaghan ug prutas. Nangaon sila kutob sa ilang gusto ug nanambok. Nagpakabuhong sila sa imong labihan nga kaayo nga gipakita kanila.

26“Apan luyo niini, misupak sila ug nagrebelde kanimo. Gitalikdan nila ang imong balaod ug gipatay nila ang imong mga propeta nga mipahimangno kanila aron sa pagpabalik kanila diha kanimo. Labihan gayod ang mga pagpasipala nga ilang gipanghimo! 27Busa gitugyan mo sila sa ilang mga kaaway nga naglisod-lisod kanila. Apan sa dihang nangayo sila ug tabang kanimo, gipamatian mo pa gihapon sila diha sa langit. Ug sa imong kalooy, gihatagan mo silag mga pangulo nga miluwas kanila gikan sa kamot sa ilang mga kaaway.

28“Apan kon maayo na ang ilang kahimtang, nagahimo na usab sila ug daotan sa imong atubangan. Unya gitugyan mo na usab sila sa kamot sa ilang mga kaaway aron dumalahan sila. Apan kon mangayo na usab sila sa imong tabang, mamati ka gihapon kanila diha sa langit. Ug sa imong kalooy ginaluwas mo sila kanunay. 29Gipahimangnoan mo sila aron motuman sila pagbalik sa imong Kasugoan. Apan nagmagahi sila ug wala nila tumana ang imong mga sugo. Nagpakasala sila batok sa imong mga sugo nga nagahatag ug tinuod nga kinabuhi sa nagatuman niini. Sa kagahi sa ilang mga ulo mitalikod sila kanimo, ug nagdumili sa pagpamati kanimo. 30Sulod sa daghang mga katuigan gipasensyahan mo sila ug gipahimangnoan sa imong Espiritu pinaagi sa mga propeta. Apan wala sila manumbaling. Busa gitugyan mo sila sa mga katawhan sa ilang palibot. 31Apan bisan pa niini, tungod sa dako mong kalooy, wala mo sila pasagdi o laglaga sa hingpit, kay maloloy-on ka nga Dios ug puno sa grasya.

32“Ikaw nga among Dios makagagahom, katingalahan, ug talahuron. Ginatuman mo ang imong kasabotan, ug ginapakita mo ang imong gugma. Karon, ayaw ipakawalay-bili ang among mga pag-antos. Nagaantos kami ug ang among mga hari, mga pangulo, mga pari, mga propeta, ug mga katigulangan, gikan pa sa panahon nga gidaog-daog kami sa mga hari sa Asiria hangtod karon. 33Matarong ang gihimo mong pagsilot kanamo. Nagmatinud-anon gayod ikaw kanamo, apan kami nagpakasala. 34Ang among mga hari, mga pangulo, mga pari, ug mga katigulangan wala motuman sa imong Kasugoan. Wala sila magtagad sa imong mga sugo ug mga pahimangno. 35Bisan aduna silay kaugalingong gingharian ug nakasinati sa imong dakong kaayo, ug bisan gihatagan mo sila sa halapad ug mabungahong yuta, wala gihapon sila moalagad kanimo o mobiya sa ilang daotang mga binuhatan. 36Mao nga karon nangaulipon kami dinhi niining yuta nga imong gihatag sa among mga katigulangan, diin makakaon unta sila sa mga abot niini ug makapahimulos sa uban pang mga kaayohan niini. 37Ang abunda nga mga abot sa yuta atua paingon sa mga hari nga gipadumala mo kanamo tungod sa among mga sala. Gihimo nila ang ilang gustong himuon kanamo ug sa among mga kahayopan. Ug labihan ang among pag-antos.”

Naghimo ug Kasabotan ang mga Tawo

38“Tungod niining tanan, kaming mga Judio naghimo ug usa ka lig-ong kasabotan. Gisulat kini ug giselyohan sa among mga pangulo, mga pari, ug mga Levita.”