Nehemiah 6 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 6:1-19

Àwọn ọ̀tá kò dáwọ́ àtakò dúró

1Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà. 2Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé: “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.”

Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi; 3Bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé; “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?” 4Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.

5Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀ 6tí a kọ sínú un rẹ̀ pé:

“A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè—Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé—ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn 7àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”

8Mo dá èsì yìí padà sí i pé: “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”

9Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.”

Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”

10Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”

11Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!” 12Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀. 13Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.

14A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí. 15Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli (oṣù kẹsànán), láàrín ọjọ́ méjìléláàdọ́ta.

Píparí odi

16Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.

17Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn. 18Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah 19Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

Swedish Contemporary Bible

Nehemja 6:1-19

Fortsatt motstånd

1När Sanvallat, Tobia, araben Geshem och våra övriga fiender fick höra att jag hade byggt upp muren, och att det inte någonstans fanns en spricka kvar, även om jag ännu inte satt in dörrar i portarna, 2sände Sanvallat och Geshem bud till mig: ”Kom, låt oss mötas i Kefirim6:2 Kefirim kan också översättas byarna. i Onodalen.” Men de hade onda avsikter mot mig. 3Jag skickade bud till dem med ett svar: ”Jag har ett stort arbete att utföra och kan inte komma. Varför skulle jag låta arbetet avbrytas för att komma och träffa er?”

4Fyra gånger sände de samma bud till mig, och varje gång gav jag dem samma svar. 5Femte gången skickade Sanvallat sin tjänare till mig med samma budskap, nu i ett brev som han hade i handen och som inte var förseglat. 6I brevet stod det:

”Det berättas bland de andra folken, och Geshem6:6 Eller Gashmu. säger det också till mig, att du och judarna tänker göra uppror och att det är därför ni bygger upp muren. Det påstås också att du tänker bli deras kung, 7och att du har tillsatt profeter som ska ropa ut om dig i Jerusalem: Det finns nu en kung i Juda! Dessa uppgifter kommer att nå kungen, så låt oss komma och rådgöra med varandra.”

8Jag skickade honom ett svar: ”Ingenting av det du säger har skett. Du har själv hittat på alltihop.”

9De försökte allesammans att skrämma oss, för de tänkte: ”De kommer att bli för svaga för arbetet, och det kommer aldrig att bli utfört.” ”Men styrk du nu mina händer!”6:9 Men styrk du nu mina händer! är av allt att döma Nehemjas bön. En annan tolkning som sammanhanget ev. skulle kunna tillåta är att Nehemja konstaterade att han i stället fortsatte med arbetet med styrkta händer, dvs. med allt större kraft.

10Jag gick sedan till Shemaja, Delajas son och Mehetavels sonson, som inte kunde lämna sitt hus6:10 Grundtextens innebörd är osäker., och han sa: ”Låt oss mötas inne i Guds hus och stänga igen templets dörrar, för de kommer för att döda dig, i natt kommer de för att döda dig.”

11”Skulle en man som jag fly?” frågade jag. ”Och skulle en man som jag kunna gå in i templet och få behålla livet. Nej, jag går inte dit.”

12Då förstod jag att han inte var sänd av Gud, utan han uttalade denna profetia mot mig därför att Tobia och Sanvallat hade lejt honom. 13Han var lejd för att jag skulle bli rädd och göra som han ville och därmed begå en synd. Det skulle skada mitt rykte så att de kunde sprida förtal om mig.

14”Min Gud, tänk på allt ont som Tobia, Sanvallat, profetissan Noadja och alla de andra profeterna gjort i sina försök att skrämma mig!”

Muren uppbyggd

15Den tjugofemte Elul blev muren färdig, efter femtiotvå dagar.

16När våra fiender hörde det och de angränsande folken såg det, blev de vanmäktiga, eftersom de förstod att det var Gud som hjälpt oss i arbetet. 17Under denna tid sände de förnäma männen i Juda många brev till Tobia och Tobia till dem. 18Det var nämligen många i Juda som var bundna till honom med en ed, därför att han var svärson till Shekanja, Aras son, och hans son Jochanan hade gift sig med en dotter till Meshullam, Berekjas son. 19De berättade för mig om hans goda gärningar, och sedan berättade de för honom vad jag sagt. Tobia skickade också brev för att skrämma mig.