Nehemiah 6 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 6:1-19

Àwọn ọ̀tá kò dáwọ́ àtakò dúró

1Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà. 2Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé: “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.”

Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi; 3Bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé; “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?” 4Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.

5Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀ 6tí a kọ sínú un rẹ̀ pé:

“A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè—Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé—ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn 7àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”

8Mo dá èsì yìí padà sí i pé: “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”

9Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.”

Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”

10Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”

11Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!” 12Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀. 13Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.

14A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí. 15Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli (oṣù kẹsànán), láàrín ọjọ́ méjìléláàdọ́ta.

Píparí odi

16Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.

17Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn. 18Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah 19Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

Священное Писание

Неемия 6:1-19

Дальнейшее противодействие строительству стены

1Когда Санбаллату, Товии, арабу Гешему и прочим нашим врагам донесли, что я отстроил стену и в ней не осталось ни одного незаделанного пролома (хотя к тому времени я ещё не поставил двери ворот), 2Санбаллат и Гешем послали сказать мне:

– Давай встретимся в одном из селений на равнине Оно.

Но они замышляли причинить мне зло, 3и я послал к ним вестников с таким ответом:

– Я занят важной работой и не могу прийти. Работа встанет, если я всё брошу и пойду к вам.

4Четыре раза они присылали ко мне с этим приглашением, и четыре раза я давал им этот ответ. 5Тогда в пятый раз Санбаллат отправил ко мне с этим же приглашением своего слугу. В руке у него было незапечатанное письмо, 6в котором было написано:

«Среди других народов ходит слух – и Гешем говорит, – что ты и иудеи замышляете восстать, и поэтому ты строишь стену. По этим слухам ты собираешься стать их царём 7и даже назначил пророков, чтобы возвещать о себе в Иерусалиме: „В Иудее есть царь!“ Этот слух дойдёт до царя. Итак, приходи, давай переговорим».

8Я послал ему ответ: «Нет никакой правды в том, что ты говоришь. Всё это ты выдумываешь сам».

9Все они старались запугать нас, думая: «Их руки очень ослабнут, чтобы делать эту работу, и она не будет завершена».

Но я молился:

– Укрепи мои руки!

10Однажды я пришёл в дом Шемаи, сына Делаи, сына Мехетавила, который заперся в своём доме.

Он сказал:

– Давай встретимся в доме Всевышнего, внутри храма, и запрём храмовые двери, потому что тебя придут убить, и придут ночью!

11Но я сказал:

– Разве такой человек, как я, может бежать? Может ли такой, как я, пойти в храм, чтобы спасти свою жизнь? Не пойду!

12Я понимал, что Всевышний не посылал его, и он пророчествовал против меня, потому что его наняли Товия и Санбаллат. 13Его наняли запугать меня, чтобы я согрешил, сделав так, а они бы лишили меня доброго имени и упрекали бы меня.

14Вспомни, Бог мой, Товию и Санбаллата по их делам; вспомни ещё и пророчицу Ноадию и прочих пророков, которые пытались запугать меня.

Завершение восстановления стены

15Стена была завершена в двадцать пятый день месяца элула (2 октября 445 г. до н. э.), за пятьдесят два дня. 16Когда об этом услышали все наши враги, все окрестные народы испугались6:16 Или: «увидели». и потеряли свою самоуверенность, потому что поняли, что эта работа была сделана с помощью нашего Бога.

17Ещё в те дни знать Иудеи посылала много писем Товии, а письма Товии приходили к ним. 18Ведь многие в Иудее были связаны с ним клятвой, потому что он был зятем Шехании, сына Араха, а его сын Иоханан женился на дочери Мешуллама, сына Берехии. 19Они даже говорили при мне о его добрых делах, а после пересказывали ему то, что я сказал. А Товия присылал письма, чтобы меня запугать.