Nehemiah 5 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 5:1-19

Nehemiah ran àwọn aláìní lọ́wọ́

1Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn. 2Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”

3Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”

4Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa. 5Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”

6Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí. 7Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí. 8Mo sì wí fún wọn pé: “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.

9Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa? 10Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró! 11Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”

12Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.”

Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí. 13Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!”

Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.

14Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀. 15Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run. 16Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.

17Síwájú sí í, àádọ́jọ (150) àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká. 18Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.

19Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.

New Russian Translation

Неемия 5:1-19

Прощение долгов беднякам

1В народе, среди мужчин и их жен, поднялся сильный ропот на своих братьев-иудеев. 2Некоторые говорили:

– Нас, наших сыновей и наших дочерей много, и чтобы кормиться и жить, нам нужно зерно.

3Другие говорили:

– Нам приходится закладывать свои поля, виноградники и дома, чтобы достать зерна во время голода.

4А были и такие, которые говорили:

– Нам приходится занимать деньги, чтобы платить царю налог на наши поля и виноградники. 5Мы из той же плоти, что и наши соплеменники, и наши сыновья такие же, как у них, но нам приходится отдавать своих сыновей и дочерей в рабство. Некоторые из наших дочерей уже порабощены, но мы бессильны, потому что наши поля и виноградники принадлежат другим.

6Услышав их ропот и эти жалобы, я очень рассердился. 7Обдумав, я обвинил знать и начальствующих. Я сказал им:

– Вы берете проценты со своих братьев!

Из-за них я созвал большое собрание 8и сказал:

– Всеми силами мы выкупали наших братьев-иудеев, которые были проданы язычникам. А теперь вы продаете своих же братьев, которых нам приходится выкупать!

Они молчали, потому что им нечего было сказать.

9Тогда я сказал:

– То, что вы делаете, – нехорошо. Разве вы не должны ходить в страхе нашего Бога, чтобы избежать порицания наших врагов-язычников? 10Я, мои братья и слуги также даем в долг народу деньги и зерно. Давайте прекратим брать проценты! 11Немедленно верните им их поля, виноградники, оливковые рощи и дома, а также проценты, которые вы им назначили, – сотую часть денег, зерна, молодого вина и масла.

12– Мы вернем это, – сказали они, – и не потребуем больше от них ничего. Мы сделаем, как ты говоришь.

Я призвал священников и заставил знать и приближенных дать клятву в том, что они выполнят обещанное. 13Еще я вытряхнул свою одежду и сказал:

– Пусть так же Бог вытряхнет всякого человека, который не сдержит этого обещания, из его дома и добра. Пусть так же этот человек будет вытряхнут и опустошен!

И все общество сказало: «Аминь!»5:13 Аминь – еврейское слово, которое переводится как «да, верно, воистину так» или «да будет так». Также в 8:6., – и прославило Бога.

И народ сделал так, как и обещал.

Неемия подает пример

14Более того, с двадцатого года правления царя Артаксеркса, когда я был назначен наместником в земле иудейской, до его тридцать второго года правления – двенадцать лет5:14 С 445 по 433 гг. до н. э. – ни я, ни братья мои не ели пищи, предназначенной для наместника. 15Прежние наместники, которые были до меня, возложили на народ тяжкое бремя и брали у них сорок шекелей5:15 Около 0,5 кг. серебра, помимо пищи и вина. Даже их слуги помыкали народом. Но я, почитая Бога, так не поступал. 16Напротив, я посвятил себя работам по восстановлению стены. Все мои слуги были собраны туда для работ; мы не покупали5:16 Так в большинстве рукописей древнееврейского текста; в некоторых рукописях, а также в ряде древних переводов: «я не покупал». земель.

17Более того, за моим столом ели сто пятьдесят иудеев и начальствующих, не считая тех, кто приходил к нам из окрестных народов. 18Каждый день у меня готовили одного быка, шесть отборных овец и птицу, а каждые десять дней в изобилии подавали всякого рода вино. Несмотря на это, я никогда не требовал пищи, предназначенной для наместника, потому что и без этого народу приходилось тяжело.

19Вспомни мне во благо, Боже мой, все, что я сделал для этого народа.