Nehemiah 5 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 5:1-19

Nehemiah ran àwọn aláìní lọ́wọ́

1Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn. 2Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”

3Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”

4Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa. 5Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”

6Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí. 7Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí. 8Mo sì wí fún wọn pé: “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.

9Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa? 10Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró! 11Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”

12Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.”

Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí. 13Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!”

Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.

14Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀. 15Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run. 16Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.

17Síwájú sí í, àádọ́jọ (150) àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká. 18Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.

19Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.

Bibelen på hverdagsdansk

Nehemiasʼ Bog 5:1-19

Nehemias taler de fattiges sag

1Kort efter begyndte nogle mænd og deres koner at klage over, at deres rige landsmænd udnyttede dem. 2Nogle sagde: „Vi har ingen penge, så vi må give vores børn i pant for at få mad.” 3Andre sagde: „Vi har pantsat vores marker, vingårde og huse for at kunne købe korn under hungersnøden.” 4Andre igen sagde: „Vi har måttet belåne vores marker og vingårde for at kunne betale skat til kongen.”

5„Hører vi ikke til samme folk?” protesterede de. „Er vores børn ikke lige så gode som deres? Det er uretfærdigt, at vi skal sælge vores børn som slaver for at kunne overleve. Vi har allerede solgt flere af vores døtre, og vi har ingen mulighed for at købe dem fri, for vores marker og vingårde tilhører pantelånerne.”

6Da jeg hørte det, blev jeg vred, 7og efter at have tænkt over sagen sagde jeg til de rige og fornemme: „Det er forkert af jer at tage pant og renter af jeres landsmænd, når I låner dem penge.” Så sammenkaldte jeg til et folkemøde og henvendte mig til de rige: 8„Vi har gjort alt, hvad vi kunne, for at frikøbe vores landsmænd, der levede som slaver hos et fremmed folk,” sagde jeg. „Men nu gør I jeres egne landsmænd til slaver! Hvor mange gange skal vi købe dem fri?” Der var dødstille. Ingen vidste, hvad de skulle svare. 9Så fortsatte jeg: „I kan ikke være bekendt at opføre jer på den måde! Har I slet ingen ærefrygt for Gud? Er det ikke nok, at vi har fjender, der udefra prøver at komme os til livs? 10Jeg og mine folk har også lånt vores nødstedte landsmænd penge og korn, men uden at kræve renter. Hold op med at tage pant og renter. 11Giv dem deres marker, vingårde, olivenlunde og huse tilbage og refunder dem, hvad I har taget i renter i form af penge, korn, vin og olie.”

12„Vi vil gøre, som du siger,” svarede de. „Vi giver dem deres ejendom tilbage og holder op med at kræve renter.” I præsternes påhør fik jeg dem så til at sværge på, at de ville gøre, som de havde sagt. 13Og mens jeg rystede min kappefold sagde jeg: „De som ikke holder, hvad de har lovet, vil Gud ryste ud fra deres hus og hjem.” „Amen!” råbte hele forsamlingen og takkede Gud. Så gik de i gang med at gøre deres ord til handling.

14I den forbindelse skal det nævnes, at i alle de 12 år, jeg var guvernør over Juda—fra kong Artaxerxes’ 20. til hans 32. regeringsår—modtog hverken jeg selv eller mine embedsmænd nogen løn eller andre ydelser fra Israels folk. 15Denne praksis stod i skærende kontrast til, hvad folket var vant til fra de tidligere guvernører, der havde udnyttet dem ved at kræve mad og vin foruden 40 sølvstykker om dagen. Desuden plejede embedsmændene også at udnytte folket. Men fordi jeg ønskede at adlyde Gud, brød jeg med den praksis. 16I stedet koncentrerede jeg mig om arbejdet på muren og nægtede at skaffe mig fast ejendom. Og alle mine embedsmænd tog del i arbejdet på lige fod med andre. 17Jeg forsørgede ellers 150 judæiske embedsmænd foruden fremmede, der kom på besøg. 18Det daglige forbrug udgjorde en okse, seks førsteklasses får og et stort antal fjerkræ. Desuden købte jeg hver tiende dag en ny forsyning vin. Alligevel undlod jeg at afkræve folket den skat, jeg havde krav på, for de havde det svært nok i forvejen.

19Min Gud, glem ikke, hvad jeg har gjort for dit folk, men velsign mig for det!