Nehemiah 4 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 4:1-23

Àtakò sí àtúnkọ́ odi Jerusalẹmu

1Nígbà tí Sanballati gbọ́ pé àwa ń tún odi náà mọ, ó bínú, ó sì bínú púpọ̀. Ó fi àwọn ará Júù ṣe ẹlẹ́yà, 2ó sọ níwájú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àti níwájú àwọn ọmọ-ogun Samaria pé, “Kí ni àwọn aláìlera Júù wọ̀nyí ń ṣe yìí? Ṣé wọn yóò mú odi wọn padà ni? Ṣé wọn yóò rú ẹbọ ni? Ṣé wọn yóò parí i rẹ̀ lóòjọ́ ni bí? Ṣé wọ́n lè mú òkúta tí a ti sun láti inú òkìtì padà bọ̀ sípò tí ó jóná bí wọ́n ṣe wà?”

3Tobiah ará Ammoni, ẹni tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, wí pé, “Ohun tí wọ́n ń mọ—bí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ lásán bá gùn ún sókè, yóò fọ́ odi òkúta wọn lulẹ̀!”

4Gbọ́ ti wa, Ọlọ́run wa, nítorí àwa di ẹni ẹ̀gàn. Dá ẹ̀gàn wọn padà sórí ara wọn. Kí o sì fi wọ́n fún ìkógun ní ilẹ̀ ìgbèkùn. 5Má ṣe bo ẹ̀bi wọn tàbí wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wọn nù kúrò níwájú rẹ, nítorí wọ́n mú ọ bínú níwájú àwọn ọ̀mọ̀lé.

6Bẹ́ẹ̀ ni àwa mọ odi náà títí gbogbo rẹ̀ fi dé ìdajì gíga rẹ̀, nítorí àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an wọn.

7Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati, Tobiah, àwọn ará Arabia, ará Ammoni, àti àwọn ènìyàn Aṣdodu gbọ́ pé àtúnṣe odi Jerusalẹmu ti ga dé òkè àti pé a ti mọ àwọn ibi tí ó yá dí, inú bí wọn gidigidi. 8Gbogbo wọn jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti wá bá Jerusalẹmu jà àti láti dìde wàhálà sí í. 9Ṣùgbọ́n àwa gbàdúrà sí Ọlọ́run wa, a sì yan olùṣọ́ ọ̀sán àti ti òru láti kojú ìhàlẹ̀ yìí.

10Lákòókò yìí, àwọn ènìyàn Juda wí pé, “Agbára àwọn òṣìṣẹ́ ti dínkù, àlàpà púpọ̀ ni ó wà tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi le è mọ odi náà.”

11Bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀tá wa wí pé, “Kí wọn tó mọ̀ tàbí kí wọn tó rí wa, àwa yóò ti dé àárín wọn, a ó sì pa wọ́n, a ó sì dá iṣẹ́ náà dúró.”

12Nígbà náà ni àwọn Júù tí ó ń gbé ní ẹ̀gbẹ́ wọn wá sọ fún wa ní ìgbà mẹ́wàá pé, “Ibikíbi tí ẹ̀yin bá padà sí, wọn yóò kọlù wá.”

13Nítorí náà mo dá ènìyàn díẹ̀ dúró níbi tí ó rẹlẹ̀ jù lẹ́yìn odi ní ibi gbangba, mo fi wọ́n síbẹ̀ nípa àwọn ìdílé wọn, pẹ̀lú àwọn idà wọn, àwọn ọ̀kọ̀ wọn àti àwọn ọrun wọn. 14Lẹ́yìn ìgbà tí mo wo àwọn nǹkan yíká, mo dìde mo sì wí fún àwọn ọlọ́lá àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù u wọn. Ẹ rántí Olúwa, ẹni tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, kí ẹ sì jà fún àwọn arákùnrin yín, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, àwọn ìyàwó yín àti àwọn ilé yín.”

15Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ pé àwa ti mọ èrò wọn àti wí pé Ọlọ́run ti bà á jẹ́, gbogbo wa padà sí ibi odi, ẹnìkọ̀ọ̀kan sí ibi iṣẹ́ tirẹ̀.

16Láti ọjọ́ náà lọ, ìdajì àwọn ènìyàn ń ṣe iṣẹ́ náà, nígbà tí àwọn ìdajì tókù múra pẹ̀lú ọ̀kọ̀, asà, ọrun àti ìhámọ́ra. Àwọn ìjòyè sì pín ara wọn sẹ́yìn gbogbo ènìyàn Juda. 17Àwọn ẹni tí ó ń mọ odi. Àwọn tí ń ru àwọn ohun èlò ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú ọwọ́ kan, wọ́n sì fi ọwọ́ kejì di ohun ìjà mú, 18olúkúlùkù àwọn ọ̀mọ̀lé fi idà wọn sí ẹ̀gbẹ́ wọn bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́. Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ń fọn ìpè dúró pẹ̀lú mi.

19Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè àti àwọn ènìyàn tókù pé, “Iṣẹ́ náà fẹ̀ ó sì pọ̀, a sì ti jìnnà sí ara wa púpọ̀ lórí odi. 20Níbikíbi tí ẹ bá ti gbọ́ ohùn ìpè, ẹ da ara pọ̀ mọ́ wa níbẹ̀. Ọlọ́run wa yóò jà fún wa!”

21Bẹ́ẹ̀ ni àwa ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú àwọn ìdajì ènìyàn tí ó di ọ̀kọ̀ mú, láti òwúrọ̀ kùtùkùtù títí di ìgbà tí ìràwọ̀ yóò fi yọ. 22Ní ìgbà náà mo tún sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn àti olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ dúró ní Jerusalẹmu ní òru, nítorí kí wọn le jẹ́ ẹ̀ṣọ́ fún wa ní òru, kí wọn sì le ṣe iṣẹ́ ní ọ̀sán.” 23Bẹ́ẹ̀ ni èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi àti àwọn ẹ̀ṣọ́ tí ó wà pẹ̀lú mi kò bọ́ aṣọ wa, olúkúlùkù wa ní ohun ìjà tirẹ̀, kódà nígbà tí wọ́n bá ń lọ pọn omi.

New Russian Translation

Неемия 4:1-23

Противодействие строительству стены

1Когда Санбаллат услышал о том, что мы строим стену, он разозлился и сильно разгневался. Он издевался над иудеями 2и перед своими союзниками и самарийским войском говорил:

– Что делают эти жалкие иудеи? Неужели они восстановят свою стену? Неужели они станут приносить жертвы? Неужели они когда-нибудь закончат строительство? Неужто они оживят камни, притом обожженные, из этих груд праха?

3Аммонитянин Товия, стоящий рядом с ним, сказал:

– Да что они там строят, если даже лисица, взобравшись на эту каменную стену, обрушит ее!

4Услышь нас, Боже наш, потому что мы в презрении. Обрати их оскорбления на их же головы. Отдай их как добычу в землю плена. 5Не покрывай их вины и грехов их не удаляй от Своих глаз, потому что они оскорбляли строителей.

6И мы строили стену, и она достигла половины своей высоты, потому что народ работал от всего сердца. 7Но когда Санбаллат, Товия, арабы с аммонитянами и жители Ашдода услышали о том, что восстановление иерусалимских стен продвигается и проломы заделываются, они очень разозлились. 8Все вместе они сговорились пойти на Иерусалим войной и устроить в нем беспорядки. 9Но мы молились нашему Богу и выставляли против них стражу днем и ночью, чтобы отвратить эту угрозу.

10А тем временем народ иудейский говорил:

– Силы носильщиков на исходе, а здесь так много мусора, что мы не можем отстраивать стену.

11А наши враги говорили:

– Прежде чем они узнают о том, что происходит, или увидят нас, мы окажемся прямо среди них, перебьем их и остановим работу.

12Иудеи, которые жили рядом с ними, приходили и раз десять говорили нам:

– Со всех сторон они пойдут на нас4:12 Возможный текст; смысл этого места в еврейском тексте неясен..

13Тогда я разместил народ за самыми низкими участками стены на открытых местах, поставив их по семьям, с мечами, копьями и луками. 14Осмотрев все, я встал и сказал знати, начальствующим и остальному народу:

– Не бойтесь их. Помните Владыку, Который велик и грозен, и сражайтесь за своих братьев, сыновей, дочерей, жен и дома.

15Когда наши враги услышали, что мы знаем об их сговоре и о том, что Бог расстроил их планы, мы все вернулись к стене, каждый – к своей работе. 16С того дня и впредь половина моих слуг трудилась на постройке, а другая половина держала копья, щиты, луки и латы. Вожди находились позади всего дома иудейского, 17который строил стену. Носильщики тяжестей делали свою работу одной рукой, а в другой держали оружие, 18и каждый из строителей во время работы был препоясан мечом. А трубач находился рядом со мной.

19И я сказал знати, начальствующим и остальному народу:

– Работа велика и обширна, и мы разбросаны по стене далеко друг от друга. 20Где бы вы ни услышали звук рога, бегите к нам туда, откуда доносится звук. Наш Бог будет сражаться за нас!

21И мы продолжали работу, и половина людей держали копья от первых лучей солнца до появления звезд. 22В то время я еще сказал народу:

– Пусть каждый человек и его помощник ночуют в Иерусалиме, чтобы они могли сторожить ночью и работать днем.

23Ни я, ни мои братья, ни мои слуги, ни стражники, которые меня сопровождали, не снимали одежд; каждый держал свое оружие, когда ходил за водой4:23 Возможный текст; смысл этого места в еврейском тексте неясен..