Nehemiah 2 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 2:1-20

Artasasta rán Nehemiah lọ Jerusalẹmu

1Ní oṣù Nisani (oṣù kẹrin) ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀. 2Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.”

Ẹ̀rù bà mí gidigidi, 3Ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”

4Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”

Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run, 5mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”

6Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.

7Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu 8Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi. 9Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.

10Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.

Nehemiah bẹ àwọn odi Jerusalẹmu wò

11Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta. 12Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.

13Ní òru, mo jáde lọ sí Àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu Ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun. 14Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá; 15Bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè Àfonífojì. 16Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.

17Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”. 18Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi.

Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.

19Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”

20Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”

New International Reader’s Version

Nehemiah 2:1-20

Artaxerxes Sends Nehemiah to Jerusalem

1Wine was brought in for King Artaxerxes. It was the month of Nisan in the 20th year of his rule. I got the wine and gave it to him. I hadn’t been sad in front of him before. But now I was. 2So the king asked me, “Why are you looking so sad? You aren’t sick. You must be feeling very sad.”

I was really afraid. 3But I said to the king, “May you live forever! Why shouldn’t I look sad? The city where my people of long ago are buried has been destroyed. And fire has burned up its gates.”

4The king said to me, “What do you want?”

I prayed to the God of heaven. 5Then I answered the king, “Are you pleased with me, King Artaxerxes? If it pleases you, send me to Judah. Let me go to the city of Jerusalem. That’s where my people are buried. I want to rebuild it.”

6The queen was sitting beside the king. He turned and asked me, “How long will your journey take? When will you get back?” It pleased the king to send me. So I chose a certain time.

7I also said to him, “If it pleases you, may I take some letters with me? I want to give them to the governors of the land west of the Euphrates River. Then they’ll help me travel safely through their territory until I arrive in Judah. 8May I also have a letter to Asaph? He takes care of the royal park. I want him to give me some logs so I can make beams out of them. I want to use them for the gates of the fort that is by the temple. Some of the logs will also be used in the city wall. And I’ll need some for the house I’m going to live in.” God was kind to me and helped me. So the king gave me what I asked for. 9Then I went to the governors of the land west of the Euphrates River. I gave them the king’s letters. He had also sent army officers and horsemen along with me.

10Sanballat and Tobiah heard about what was happening. Sanballat was a Horonite. Tobiah was an official from Ammon. They were very upset that someone had come to help the Israelites.

Nehemiah Checks Out the Walls of Jerusalem

11I went to Jerusalem and stayed there for three days. 12Then at night I took a few other people with me to check out the walls. I hadn’t told anyone what my God wanted me to do for Jerusalem. There weren’t any donkeys with me except the one I was riding on.

13That night I went out through the Valley Gate. I went toward the Jackal Well and the Dung Gate. I checked out the walls of Jerusalem. They had been broken down. I also checked the city gates. Fire had burned them up. 14I moved on toward the Fountain Gate and the King’s Pool. But there wasn’t enough room for my donkey to get through. 15It was still night. I went up the Kidron Valley. I kept checking the wall. Finally, I turned back. I went back in through the Valley Gate. 16The officials didn’t know where I had gone or what I had done. That’s because I hadn’t said anything to anyone yet. I hadn’t told the priests or nobles or officials. And I hadn’t spoken to any other Jews who would be rebuilding the wall.

17I said to them, “You can see the trouble we’re in. Jerusalem has been destroyed. Fire has burned up its gates. Come on. Let’s rebuild the wall of Jerusalem. Then people won’t be ashamed anymore.” 18I also told them how my gracious God was helping me. And I told them what the king had said to me.

They replied, “Let’s start rebuilding.” So they began that good work.

19But Sanballat, the Horonite, heard about it. So did Tobiah, the official from Ammon. Geshem, the Arab, heard about it too. All of them laughed at us. They made fun of us. “What do you think you are doing?” they asked. “Are you turning against the king?”

20I answered, “The God of heaven will give us success. We serve him. So we’ll start rebuilding the walls. But you don’t have any share in Jerusalem. You don’t have any claim to it. You don’t have any right to worship here.”