Nehemiah 2 – YCB & GKY

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 2:1-20

Artasasta rán Nehemiah lọ Jerusalẹmu

1Ní oṣù Nisani (oṣù kẹrin) ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀. 2Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.”

Ẹ̀rù bà mí gidigidi, 3Ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”

4Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”

Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run, 5mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”

6Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.

7Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu 8Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi. 9Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.

10Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.

Nehemiah bẹ àwọn odi Jerusalẹmu wò

11Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta. 12Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.

13Ní òru, mo jáde lọ sí Àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu Ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun. 14Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá; 15Bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè Àfonífojì. 16Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.

17Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”. 18Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi.

Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.

19Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”

20Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”

Holy Bible in Gĩkũyũ

Nehemia 2:1-20

Aritashashita Gũtũma Nehemia Jerusalemu

12:1 Ezar 4:7Mweri-inĩ wa Nisani, mwaka wa mĩrongo ĩĩrĩ wa Mũthamaki Aritashashita, rĩrĩa aareheirwo ndibei, ngĩoya ndibei ĩyo ngĩmĩnengera mũthamaki. Mbere ya hĩndĩ ĩyo ndiatukĩtie gĩthiithi ndĩ harĩ we; 2nĩ ũndũ ũcio mũthamaki akĩnjũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte ũtukie gĩthiithi ũguo na ndũrĩ mũrũaru? Ũndũ ũcio no uumanire na kĩeha kĩa ngoro.”

Na niĩ ngĩĩtigĩra mũno, 32:3 1Ath 1:31; Thab 137:6no ngĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Mũthamaki arotũũra nginya tene! Gĩthiithi gĩakwa kĩngĩaga gũtuka atĩa hĩndĩ ĩrĩa itũũra inene rĩrĩa maithe makwa mathikĩtwo rĩkirĩte ihooru, na ihingo ciarĩo igacinwo ikaniinwo na mwaki?”

4Mũthamaki akĩnjũũria atĩrĩ, “Ũkwenda atĩa?”

Hĩndĩ ĩyo ngĩhooya Ngai wa Igũrũ, 5na ngĩcookeria mũthamaki atĩrĩ, “Mũthamaki, angĩona kwagĩrĩire, na ndungata yaku ĩtĩkĩrĩke maitho-inĩ make, nĩakĩndũme itũũra rĩu inene rĩa Juda, kũrĩa maithe makwa mathikĩtwo, nĩguo ngarĩake rĩngĩ.”

62:6 Neh 5:14; 13:6Hĩndĩ ĩyo mũthamaki, aikaranĩtie na mũtumia wake, akĩnjũũria atĩrĩ, “Rũgendo rwaku nĩ rwa matukũ maigana na ũgaacooka rĩ?” Mũthamaki akĩona arĩ wega andũme; nĩ ũndũ ũcio ngĩtua ihinda rĩa gũthiĩ.

72:7 Ezar 8:36Ningĩ ngĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthamaki angĩona kwagĩrĩire, reke heo marũa ndwarĩre abarũthi a Mũrĩmo-wa-Farati, nĩgeetha manjĩtĩkĩrie hĩtũkĩre kuo kinya nginye Juda. 82:8 Neh 7:2; Ezar 4:24O na no heo marũa ndwarĩre Asafu, mũmenyereri wa mũtitũ wa mũthamaki, nĩgeetha akaahe mbaũ cia gũthondeka mĩgamba ya ihingo cia nyũmba ya ũthamaki ĩrĩa ĩriganĩtie na hekarũ, na cia gwaka rũthingo rwa itũũra inene o na cia gwaka nyũmba ĩrĩa ndĩrĩikaraga?” Na tondũ ũtugi wa guoko kwa Ngai wakwa warĩ hamwe na niĩ, mũthamaki agĩĩtĩkĩra kũũhingĩria maũndũ marĩa mothe ndaamũũrĩtie. 9Nĩ ũndũ ũcio ngĩthiĩ kũrĩ abarũthi a Mũrĩmo-wa-Farati, ngĩmanengera marũa ma mũthamaki. Ningĩ mũthamaki nĩatũmĩte anene a mbũtũ cia ita hamwe na thigari iria ithiiaga na mbarathi tũthiĩ hamwe nao.

102:10 Neh 4:1, 7Rĩrĩa Sanibalati ũrĩa Mũhoroni,2:10 Sanibalati aarĩ barũthi wa Samaria. na Tobia mũnene ũrĩa Mũamoni, maaiguire ũhoro ũcio, magĩtangĩka mũno makĩria nĩkũigua atĩ kwarĩ mũndũ wokĩte gũcaria maũndũ ma kũguna andũ a Isiraeli.

Nehemia Kũrora Thingo cia Jerusalemu

112:11 Kĩam 40:13Nĩndathiire Jerusalemu, na thuutha wa gũikara kuo mĩthenya ĩtatũ-rĩ, 12ngiumagara ũtukũ ndĩ na andũ matarĩ aingĩ. Ndierĩte mũndũ o na ũmwe ũndũ ũrĩa Ngai wakwa eekĩrĩte ngoro-inĩ yakwa njĩke nĩ ũndũ wa Jerusalemu. Gũtiarĩ na mbarathi ingĩ tiga ĩrĩa yanguuĩte.

132:13 2Maũ 26:9Nĩndathiire ũtukũ ngereire Kĩhingo gĩa Kĩanda,2:13 Kĩhingo gĩa Kĩanda kĩarĩ mwena wa ithũĩro wa rũthingo rwa Jerusalemu. njerekeire Gĩthima kĩa Ndamathia na Kĩhingo gĩa Kĩara-inĩ,2:13 Kĩhingo gĩa Kĩara-inĩ nĩkĩo Ayahudi moimagĩria nyamũ iria ciarutagwo magongona, magacitwara Gĩtuamba-inĩ kĩa Beni-Hinomu. ngĩroraga thingo cia Jerusalemu iria ciamomoretwo, na ihingo ciarĩo iria ciacinĩtwo ikaniinwo nĩ mwaki. 142:14 Neh 3:15; 12:37; 2Ath 18:17Ningĩ ngĩthiĩ o na mbere njerekeire Kĩhingo gĩa Gĩthima na Karia-inĩ ka Mũthamaki, no hatiarĩ handũ haiganu ha kũhĩtũkĩrwo nĩ mbarathi yakwa; 15nĩ ũndũ ũcio ngĩambata na mũkuru ũtukũ ngĩroraga ũrĩa rũthingo rwatariĩ. Ndakinya mũthia, ngĩhũndũka ngĩingĩrĩra Kĩhingo gĩa Kĩanda rĩngĩ. 16Anene a kũu matiamenyire kũrĩa ndathiĩte kana ũrĩa ndekaga tondũ ndiamenyithĩtie Ayahudi, kana athĩnjĩri-Ngai, kana arĩa maarĩ igweta, kana anene, o na kana arĩa angĩ mangĩarutire wĩra.

172:17 Neh 1:3; Isa 58:12Ningĩ ngĩmeera atĩrĩ, “Nĩmũrona thĩĩna ũrĩa tũrĩ naguo: itũũra rĩa Jerusalemu nĩrĩanangĩku, na ihingo ciarĩo igacinwo na mwaki. Ũkai twake rũthingo rwa Jerusalemu rĩngĩ, na tũtigacooka kũnyararwo o na rĩ.” 18O na ningĩ ngĩmeera ũrĩa guoko kwa ũtugi kwa Ngai wakwa kwarĩ hamwe na niĩ, na ũrĩa mũthamaki anjĩĩrĩte.

Nao magĩcookia atĩrĩ, “Nĩtwambĩrĩriei gwaka rĩngĩ.” Nĩ ũndũ ũcio makĩambĩrĩria wĩra ũcio mwega.

19No rĩrĩa Sanibalati ũrĩa Mũhoroni na Tobia mũnene ũrĩa Mũamoni na Geshemu ũrĩa Mũarabu maiguire ũhoro ũcio, magĩtũnyũrũria na magĩtũthekerera, makĩũria atĩrĩ, “Nĩ atĩa ũũ mũreka? Kaĩ mũkũremera mũthamaki?”

202:20 Ezar 4:3; Atũm 8:21Ngĩmacookeria atĩrĩ, “Ngai wa Igũrũ nĩwe ũgũtũma tũgaacĩre. Ithuĩ ndungata ciake nĩtũkwambĩrĩria gwaka rĩngĩ, no ha ũhoro wanyu-rĩ, mũtirĩ na igai gũkũ Jerusalemu, kana kĩhooto, kana ũndũ wa tene wa kũmũnyiitithania narĩo.”