Nehemiah 11 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 11:1-36

Àwọn olùgbé tuntun ní Jerusalẹmu

1Nísinsin yìí àwọn olórí àwọn ènìyàn tẹ̀dó sí Jerusalẹmu, àwọn ènìyàn tókù sì dìbò láti mú ẹnìkọ̀ọ̀kan jáde nínú àwọn mẹ́wàá mẹ́wàá láti máa gbé ní Jerusalẹmu, ìlú mímọ́, nígbà tí àwọn mẹ́sàn-án tókù yóò dúró sí àwọn ìlú u wọn. 2Àwọn ènìyàn súre fún gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n jọ̀wọ́ ara wọn láti gbé ní Jerusalẹmu.

311.3-22: 1Ki 9.2-34.Wọ̀nyí ni àwọn olórí agbègbè ìjọba tí wọ́n tẹ̀dó sí Jerusalẹmu (díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ìran àwọn ìránṣẹ́ Solomoni ń gbé àwọn ìlú Juda, olúkúlùkù ń gbé lórí ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní àwọn ìlú náà. 4Nígbà tí àwọn ènìyàn tókù nínú àwọn Juda àti Benjamini ń gbé ní Jerusalẹmu):

Nínú àwọn ọmọ Juda:

Ataiah ọmọ Ussiah ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatia, ọmọ Mahalaleli, ìran Peresi;

5àti Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Koli-Hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣilo.

6Àwọn ìran Peresi tó gbé ní Jerusalẹmu jẹ́ àádọ́rin lé nírínwó ó dín méjì (468) alágbára ọkùnrin.

7Nínú àwọn ìran Benjamini:

Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Joedi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jeṣaiah, 8àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, Gabbai àti Sallai jẹ́ ọ̀rìn-dínlẹ́gbẹ̀rún ó-lé-mẹ́jọ (928) ọkùnrin.

9Joeli ọmọ Sikri ni olórí òṣìṣẹ́ wọn, Juda ọmọ Hasenuah sì ni olórí agbègbè kejì ní ìlú náà.

10Nínú àwọn àlùfáà:

Jedaiah; ọmọ Joiaribu; Jakini;

11Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, àwọn ni olórí tó ń bojútó ilé Ọlọ́run, 12àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, ẹni tí ó ń ṣe iṣẹ́ ní tẹmpili jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó-lé-mẹ́rinlélógún (822) ọkùnrin:

Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaiah, ọmọ Amisi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah, 13àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí ìdílé jẹ́ òjìlúgba ó-lé-méjì (242) ọkùnrin:

Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahsai, ọmọ Meṣilemoti, ọmọ Immeri, 14àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin jẹ́ méjì-dínláàdọ́je (128).

Olórí òṣìṣẹ́ ẹ wọn ni Sabdieli ọmọ Hagedolimu.

15Láti inú àwọn ọmọ Lefi:

Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ọmọ Bunni;

16Ṣabbetai àti Josabadi, olórí méjì nínú àwọn ọmọ Lefi, àwọn tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ tí ó wà ní ẹ̀yìn àgbàlá ilé Ọlọ́run;

17Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, adarí tí ó ń ṣáájú ìdúpẹ́ àti àdúrà;

Bakbukiah ẹnìkejì láàrín àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀;

àti Abida ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.

18Àwọn ọmọ Lefi nínú ìlú mímọ́ jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó-lé-mẹ́rin (284).

19Àwọn aṣọ́nà:

Akkubu, Talmoni, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n máa ń ṣọ́nà jẹ́ méjìléláàdọ́-sàn-án (172) ọkùnrin.

20Àwọn tókù nínú àwọn ọmọ Israẹli, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, wà ní gbogbo ìlú u Juda, olúkúlùkù lórí ilẹ̀ ìní tirẹ̀.

21Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili ń gbé lórí òkè Ofeli, Ṣiha àti Giṣpa sì ni alábojútó wọn.

22Olórí òṣìṣẹ́ àwọn ọmọ Lefi ní Jerusalẹmu ní Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah ọmọ Mika. Ussi jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ìran Asafu tí wọ́n jẹ́ akọrin ojúṣe nínú ìjọ́sìn ní ilé Ọlọ́run. 23Àwọn akọrin wà ní abẹ́ àṣẹ ọba, èyí tí ó n díwọ̀n iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn.

24Petahiah ọmọ Meṣesabeli, ọ̀kan nínú àwọn Sera ọmọ Juda ní aṣojú ọba nínú ohun gbogbo tí ó jẹ mọ́ ti àwọn ènìyàn náà.

25Fún ìletò pẹ̀lú oko wọn, díẹ̀ nínú àwọn ènìyàn Juda tí ń gbé Kiriati-Arba, àti àwọn ìletò agbègbè e rẹ̀, ní Diboni àti ìletò rẹ̀, ní Jekabseeli. 26Ní Jeṣua, ní Molada, ní Beti-Peleti 27Ní Hasari-Ṣuali, ní Beerṣeba àti àwọn agbègbè rẹ̀. 28Ní Siklagi, ní Mekona àti àwọn ìletò rẹ̀, 29ní Ẹni-Rimoni, ní Sora, ní Jarmatu, 30Sanoa, Adullamu àti àwọn ìletò o wọn, ní Lakiṣi àti àwọn oko rẹ̀, àti ní Aseka àti àwọn ìletò rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé láti Beerṣeba títí dé Àfonífojì Hinnomu.

31Àwọn ọmọ Benjamini láti Geba ń gbé ní Mikmasi, Aija, Beteli àti àwọn ìletò rẹ̀. 32Ní Anatoti, Nobu àti Ananiah, 33ní Hasori Rama àti Gittaimu, 34ní Hadidi, Ṣeboimu àti Neballati, 35ní Lodi àti Ono, àti ní Àfonífojì àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà.

36Nínú ìpín àwọn ọmọ Lefi ni Juda tẹ̀dó sí Benjamini.

La Bible du Semeur

Néhémie 11:1-36

Le repeuplement de Jérusalem et l’organisation de la ville

1Les chefs du peuple s’installèrent à Jérusalem. Pour le reste du peuple, on tira au sort pour faire venir s’établir à Jérusalem, la ville sainte, une famille sur dix. Les neuf autres pouvaient rester dans les autres localités. 2Certains hommes s’offrirent volontairement pour habiter à Jérusalem. Leurs compatriotes les bénirent. 3Dans les villes de Juda habitaient les Israélites, les prêtres, les lévites, les desservants du Temple et les descendants des serviteurs de Salomon, chacun dans sa propriété et sa ville respective. Et voici la liste des chefs de la province qui se fixèrent à Jérusalem. 4De plus, des gens des tribus de Juda et de Benjamin s’établirent à Jérusalem : De la tribu de Juda : Ataya, fils d’Ozias, ayant pour descendants : Zacharie, Amaria, Shephatia, Mahalaléel, de la lignée de Pérets, 5et Maaséya, fils de Baruch, dont les ascendants étaient Kol-Hozé, Hazaya, Adaya, Yoyarib, Zacharie et Shiloni. 6Les descendants de Pérets qui s’établirent à Jérusalem furent en tout 468 hommes d’âge adulte.

7Membres de la tribu de Benjamin : Sallou, fils de Meshoullam, qui avait pour ascendants : Yoëd, Pedaya, Kolaya, Maaséya, Itiel et Esaïe. 8Il y avait en outre Gabbaï et Sallaï. Cela fait en tout 928 hommes. 9Joël, fils de Zikri, était leur responsable ; et Juda, fils de Hassenoua, était l’adjoint de la ville.

10Parmi les prêtres : Yedaeya, fils de Yoyarib, Yakîn, 11Seraya, fils de Hilqiya, qui avait pour ascendants Meshoullam, Tsadoq, Merayoth et Ahitoub, responsable en chef du temple de Dieu. 12822 membres de son lignage étaient occupés au service du Temple. Il y avait aussi Adaya, fils de Yeroham, qui avait pour ascendants Pelalia, Amtsi, Zacharie, Pashhour et Malkiya, 13ainsi que 242 chefs de groupes familiaux de sa lignée. Il y avait Amashsaï, fils d’Azaréel, dont les ascendants étaient Ahzaï, Meshillémoth, Immer. 14Avec les autres hommes valeureux de sa lignée, ils étaient au nombre de 128. Zabdiel, fils de Guedolim, en était le chef. 15Parmi les lévites, Shemaya, fils de Hashoub, descendant d’Azriqam, d’Hashabia et de Bounni, 16Shabthaï et Yozabad, qui faisaient partie des chefs des lévites, étaient chargés des travaux extérieurs du Temple. 17Mattania, fils de Michée, descendant de Zabdi, descendant d’Asaph, qui était responsable d’entonner la louange lors de la prière, Baqbouqia, le second parmi ses frères, et Abda, fils de Shammoua, descendant de Galal et Yedoutoun. 18284 lévites habitaient la ville sainte. 19Il y avait encore 172 portiers, chargés de surveiller les portes : Aqqoub et Talmôn, et les membres de leur groupe familial. 20Le reste des Israélites, des prêtres et des lévites étaient établis dans toutes les villes de Juda, chacun dans son patrimoine. 21Les desservants du Temple habitaient le quartier de l’Ophel11.21 Voir 3.26 et note.. Tsiha et Guishpa étaient leurs chefs.

22Le responsable des lévites à Jérusalem était Ouzzi, fils de Bani, qui avait pour ascendants Hashabia, Mattania et Michée, descendants d’Asaph. Les descendants d’Asaph étaient les musiciens chargés du service musical dans le Temple. 23Ils étaient soumis à des ordonnances royales qui réglaient leur activité jour par jour.

24Petahya, fils de Meshézabéel, de la lignée de Zérah, fils de Juda, était le délégué du roi pour toutes les affaires civiles.

Les localités repeuplées par des Judéens

25D’autres membres de la tribu de Juda s’établirent dans les localités de la campagne à Qiryath-Arba11.25 C’est-à-dire Hébron (voir Gn 23.2 ; Jos 15.54). et les villages qui en dépendent, à Dibôn et les villages qui en dépendent, à Yeqabtséel et les localités qui en dépendent, 26à Yéshoua, à Molada, à Beth-Paleth ; 27à Hatsar-Shoual, à Beer-Sheva et les villages qui en dépendent, 28à Tsiqlag, à Mekona et les villages qui en dépendent, 29à Eyn-Rimmôn, à Tsorea, à Yarmouth, 30à Zanoah, à Adoullam et les localités qui en dépendent, à Lakish et les fermes des environs, à Azéqa et les villages qui en dépendent. Ils occupèrent ainsi toute la région depuis Beer-Sheva jusqu’à la vallée de Hinnom.

31Les membres de la tribu de Benjamin occupèrent Guéba, Mikmas, Aya, Béthel et les villages qui en dépendent, 32Anatoth, Nob, Anania, 33Hatsor, Rama, Guittaïm, 34Hadid, Tseboïm, Neballath, 35Lod et Ono, la vallée des Artisans.

36Certains groupes de lévites de Juda allèrent s’installer parmi les Benjaminites.