Nehemiah 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Nehemiah 1:1-11

Àdúrà Nehemiah

1Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah:

Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa, 2Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.

3Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”

4Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run. 5Nígbà náà ni mo wí pé:

Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́. 6Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ. 7Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.

8“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè. 9Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’

10“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ. 11Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì ṣíjú àánú wò ó níwájú Ọkùnrin yìí.”

Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.

Nouă Traducere În Limba Română

Neemia 1:1-11

Rugăciunea lui Neemia

1Cuvintele lui Neemia, fiul lui Hacalia.

În luna Chislev1 Luna a noua în calendarul babilonian, ce corespunde lunilor noiembrie-decembrie., în al douăzecilea an, în timp ce mă aflam în citadela Susei, 2unul din frații mei, Hanani, a sosit din Iuda împreună cu câțiva bărbați. I‑am întrebat despre iudeii care supraviețuiseră, cei rămași după captivitate, și despre Ierusalim. 3Ei mi‑au răspuns: „Supraviețuitorii, cei care au rămas după captivitate, sunt acolo, în provincie, în necaz mare și rușine! Zidul Ierusalimului este dărâmat, iar porțile lui sunt arse de foc.“

4Când am auzit aceste lucruri, m‑am așezat jos, am plâns și am bocit câteva zile. Am postit și m‑am rugat Dumnezeului cerurilor, 5zicând:

„Oh, Doamne, Dumnezeul cerurilor, Dumnezeule mare și de temut, Cel Care Își ține legământul și îndurarea5 Ebr.: hesed, termen care apare frecvent (de peste 250 ori) în VT, având o varietate de sensuri (îndurare, bunătate, bunăvoință, milă, credincioșie, dragoste statornică). Se referă atât la relațiile dintre oameni, cât și, într‑un mod cu totul special, la relația dintre YHWH și Israel. Cel mai frecvent, se referă la loialitatea părților implicate în legământ (în special loialitatea lui YHWH, care este certă). Termenul, așa cum o dovedește varietatea de sensuri, cuprinde toate implicațiile loialității lui YHWH față de promisiunile legământului. Sau: Își păstrează cu loialitate legământul; sau Își păstrează legământul dragostei. față de cei ce‑L iubesc și păzesc poruncile Lui, 6Te rog, să ia aminte urechea Ta și ochii Tăi să fie deschiși, ca să asculți rugăciunea pe care robul Tău o rostește acum înaintea Ta, zi și noapte, cu privire la fiii lui Israel, robii Tăi. Mărturisesc păcatele fiilor lui Israel, pe care noi le‑am săvârșit față de Tine. Atât eu, cât și familia mea am păcătuit. 7Te‑am jignit și nu am păzit poruncile, hotărârile și judecățile pe care Tu le‑ai poruncit lui Moise, robul Tău. 8Te rog, adu‑Ți aminte de cuvântul pe care i l‑ai poruncit lui Moise, robul Tău, zicând: «Dacă veți fi necredincioși, vă voi împrăștia printre popoare, 9dar, dacă vă veți întoarce la Mine, dacă veți păzi poruncile Mele și le veți împlini, chiar dacă veți fi alungați la capătul cerului și de acolo vă voi aduna și vă voi aduce în locul unde am ales să locuiască Numele Meu.» 10Ei sunt robii Tăi și poporul Tău, pe care l‑ai răscumpărat cu puterea Ta cea mare și cu brațul Tău cel puternic. 11Oh, Stăpâne, Te rog, să ia aminte urechea Ta la rugăciunea robului Tău și la rugăciunea robilor Tăi care‑și găsesc plăcerea în a se teme de Numele Tău. Te rog, fă să reușească robul Tău astăzi! Fă să capăt îndurare înaintea acestui om!“

Pe atunci eram paharnicul împăratului.