Mika 5 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 5:1-15

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu

1Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,

ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,

nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.

Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.

2“Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,

bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,

nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli

yóò ti jáde tọ̀ mí wá,

ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà láéláé.”

3Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá

títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,

àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà

láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.

4Òun yóò sì dúró,

yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa,

ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.

Wọn yóò sì wà láìléwu,

nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ

yóò sì dé òpin ayé.

Ìgbàlà àti ìparun

5Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.

Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,

nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,

àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.

6Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,

àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.

Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria

nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.

7Ìyókù Jakọbu yóò sì wà

láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn

bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa,

bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,

tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn

tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.

8Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà

ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,

bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,

bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,

èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,

tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,

tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.

9A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,

gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ

èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.

11Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,

èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.

12Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,

ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.

13Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,

àti ọwọ́n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;

ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀

fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.

14Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,

èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.

15Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú

lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”

Persian Contemporary Bible

ميكاه 5:1-15

1ای لشكر اورشليم آماده شويد، زيرا شهر محاصره شده است! دشمن به رهبر اسرائيل ضربه خواهد زد.

وعدهٔ ظهور رهبری از بيت‌لحم

2خداوند می‌فرمايد: «ای بيت‌لحم افراته، هر چند كه در يهودا روستای كوچكی بيش نيستی با وجود اين از تو كسی برای من ظهور خواهد كرد كه از ازل بوده است و او قوم من اسرائيل را رهبری خواهد نمود.» 3خدا قوم خود را به دست دشمن تسليم خواهد كرد تا زمانی كه زن حامله فرزند خود را به دنيا آورد5‏:3 اشاره‌ای است به تولد مسيح از مريم باکره. نگاه کنيد به اشعيا 7‏:14.‏. آنگاه بقيهٔ قوم اسرائيل كه در اسارت هستند باز خواهند گشت و به برادران خود ملحق خواهند شد. 4وقتی او بيايد با قوت و جلال خداوند، خدای خود گلهٔ خود را خواهد چرانيد. قوم او در امنيت زندگی خواهند كرد، زيرا تمام مردم جهان به عظمت او پی خواهند برد، 5و او صلح و سلامتی به ارمغان خواهد آورد. هنگامی كه آشوری‌ها به سرزمين ما هجوم آورده، وارد قلعه‌هايمان شوند، رهبران نيرومند خود را به مقابلهٔ آنها خواهيم فرستاد؛ 6و ايشان با شمشيرهای از غلاف كشيده، آشور، سرزمين «نمرود» را فتح خواهند كرد. زمانی كه آشوری‌ها به سرزمين ما حمله‌ور شوند، او ما را از دست ايشان خواهد رهانيد.

7آنگاه بازماندگان قوم اسرائيل برای قومهای بسيار، شبنم و بارانی از جانب خداوند خواهند بود. آنها به خدا اعتماد خواهند داشت نه به انسان. 8ايشان در ميان قومها مانند شير درنده در ميان گله‌های گوسفند خواهند بود، كه هنگام عبور پايمال می‌كند و می‌درد و كسی نمی‌تواند مانع او شود. 9قوم اسرائيل در برابر دشمنانش خواهد ايستاد و آنها را نابود خواهد كرد.

مجازات قوم اسرائيل

10خداوند به قوم اسرائيل می‌فرمايد: «در آن زمان تمام اسبها و عرابه‌های شما را از بين خواهم برد، 11شهرهای شما را خراب نموده، همهٔ قلعه‌هايتان را ويران خواهم كرد. 12به جادوگری شما پايان خواهم داد و ديگر فالگيرانی نخواهند بود تا با آنها مشورت كنيد. 13تمام بتهای شما را سرنگون خواهم ساخت. ديگر هرگز آنچه را كه با دست خود ساخته‌ايد عبادت نخواهيد كرد. 14بتهايی را كه در سرزمين شماست منهدم خواهم كرد و شهرهايتان را با خاک يكسان خواهم نمود.

15«من با خشم و غضب از اقوامی كه مرا اطاعت نمی‌كنند انتقام خواهم گرفت.»