Mika 5 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 5:1-15

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu

1Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,

ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,

nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.

Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.

2“Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,

bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,

nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli

yóò ti jáde tọ̀ mí wá,

ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà láéláé.”

3Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá

títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,

àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà

láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.

4Òun yóò sì dúró,

yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa,

ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.

Wọn yóò sì wà láìléwu,

nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ

yóò sì dé òpin ayé.

Ìgbàlà àti ìparun

5Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.

Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,

nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,

àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.

6Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,

àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.

Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria

nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa

tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.

7Ìyókù Jakọbu yóò sì wà

láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn

bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa,

bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,

tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn

tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.

8Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà

ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,

bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,

bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,

èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,

tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,

tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.

9A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,

gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.

10“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ

èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.

11Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,

èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.

12Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,

ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.

13Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,

àti ọwọ́n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;

ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀

fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.

14Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,

èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.

15Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú

lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”

Nueva Versión Internacional

Miqueas 5:1-15

Humillación y exaltación de la dinastía davídica

1Ahora, reúne tus tropas, ciudad guerrera,

porque nos asedian.

Con vara golpearán en la mejilla

al gobernante de Israel.

2Pero tú, Belén Efrata,

pequeña entre los clanes de Judá,

de ti saldrá el que gobernará a Israel;

sus orígenes son de un pasado distante,

desde tiempos antiguos.

3Por eso Dios los entregará al enemigo

hasta que tenga su hijo la que va a ser madre

y vuelva junto al pueblo de Israel

el resto de sus hermanos.

4Él se establecerá y los pastoreará

con el poder del Señor,

con la majestad del nombre del Señor su Dios.

Vivirán seguros, porque él dominará

hasta los confines de la tierra.

5¡Él será nuestra paz!

Si Asiria llegara a invadir nuestro país

para pisotear nuestras fortalezas,

le haremos frente con siete pastores

y aun con ocho príncipes del pueblo.

6Ellos pastorearán a Asiria con la espada

y a la tierra de Nimrod con la daga.5:6 con la daga. Alt. en sus puertas.

Si Asiria llegara a invadir nuestro país,

si llegara a cruzar nuestras fronteras,

¡él nos rescatará!

El remanente

7El remanente de Jacob será,

en medio de muchos pueblos,

como rocío que viene del Señor,

como abundante lluvia sobre la hierba,

que no depende de los hombres

ni espera nada de ellos.

8El remanente de Jacob será,

entre las naciones,

en medio de muchos pueblos,

como un león entre los animales del bosque,

como un leoncillo entre las ovejas del rebaño,

que al pasar las pisotea y las desgarra

sin que nadie pueda rescatarlas.

9Levantarás la mano contra tus enemigos

y acabarás con todos tus agresores.

Purificación de un pueblo idólatra y belicoso

10«En aquel día», afirma el Señor,

«exterminaré tu caballería

y destruiré tus carros de guerra.

11Exterminaré las ciudades de tu país

y derribaré todas tus fortalezas.

12Pondré fin a tus hechicerías

y no tendrás más adivinos.

13Acabaré con tus ídolos

y con tus piedras sagradas;

nunca más volverás a postrarte

ante las obras de tus manos.

14Arrancaré tus imágenes de Aserá

y reduciré a escombros tus ciudades;

15con ira y con furor me vengaré

de las naciones que no me obedecieron».