Mika 3 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 3:1-12

Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí

1Nígbà náà, ni mo wí pé,

“Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,

ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.

Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.

2Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;

Ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn

àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;

3Àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,

wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.

Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;

Wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,

bí ẹran inú agbada?”

4Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa,

Ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.

Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,

nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Ní ti àwọn Wòlíì

tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,

tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,

wọn yóò kéde àlàáfíà;

Ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,

wọn yóò múra ogun sí i.

6Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,

tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,

òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,

tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀

Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì

ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.

7Ojú yóò sì ti àwọn Wòlíì

àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.

Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,

nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

8Ṣùgbọ́n ní tèmi,

èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa,

láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,

àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.

9Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,

àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,

tí ó kórìíra òdodo

tí ó sì yí òtítọ́ padà;

10Tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,

àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.

11Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,

àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà

àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.

Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé,

“Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa!

Ibi kan kì yóò bá wa.”

12Nítorí náà, nítorí tiyín,

ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,

Jerusalẹmu yóò sì di ebè

àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

Nueva Versión Internacional

Miqueas 3:1-12

El castigo a los gobernantes corruptos

1Entonces dije:

«Escuchen, príncipes de Jacob,

autoridades del pueblo de Israel:

¿Acaso no corresponde a ustedes

conocer el derecho?

2Ustedes odian el bien y aman el mal;

a mi pueblo le arrancan la piel del cuerpo

y la carne de los huesos.

3Ustedes se comen la carne de mi pueblo,

le arrancan la piel y rompen sus huesos;

lo descuartizan como carne para la olla,

como carne para el caldero».

4Entonces pedirán auxilio al Señor,

pero él no responderá;

esconderá de ellos su rostro

porque hicieron lo malo.

Contraste entre el profeta falso y el verdadero

5Esto es lo que dice el Señor contra ustedes,

profetas que desvían a mi pueblo:

«Con el estómago lleno, invitan a la paz;

con el vientre vacío, declaran la guerra.

6Por tanto, tendrán noches sin visiones,

oscuridad sin adivinaciones».

El sol se ocultará de estos profetas;

el día se les volverá tinieblas.

7Los videntes quedarán en vergüenza;

los adivinos serán humillados.

Cubrirán sus rostros,

pues no habrá respuesta de Dios.

8Yo, en cambio, estoy lleno de poder,

del Espíritu del Señor,

de justicia y de fuerza,

para echarle en cara a Jacob su delito;

para reprocharle a Israel su pecado.

El gobierno corrupto, causa de la caída de Sión

9Escuchen esto ustedes,

príncipes de la casa de Jacob

y autoridades del pueblo de Israel,

que abominan la justicia y tuercen el derecho,

10que edifican a Sión con sangre

y a Jerusalén con maldad.

11Sus jueces juzgan por soborno,

sus sacerdotes instruyen por paga

y sus profetas predicen por dinero;

para colmo, buscan apoyo en el Señor, diciendo:

«¿No está el Señor entre nosotros?

¡No vendrá sobre nosotros ningún mal!».

12Por lo tanto, por culpa de ustedes

Sión será como un campo arado;

Jerusalén quedará en ruinas

y el monte del Templo se volverá un matorral.