Mika 3 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 3:1-12

Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí

1Nígbà náà, ni mo wí pé,

“Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,

ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.

Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.

2Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;

Ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn

àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;

3Àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,

wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.

Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;

Wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,

bí ẹran inú agbada?”

4Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa,

Ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.

Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,

nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Ní ti àwọn Wòlíì

tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,

tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,

wọn yóò kéde àlàáfíà;

Ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,

wọn yóò múra ogun sí i.

6Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,

tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,

òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,

tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀

Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì

ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.

7Ojú yóò sì ti àwọn Wòlíì

àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.

Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,

nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

8Ṣùgbọ́n ní tèmi,

èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa,

láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,

àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.

9Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,

àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,

tí ó kórìíra òdodo

tí ó sì yí òtítọ́ padà;

10Tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,

àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.

11Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,

àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà

àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.

Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé,

“Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa!

Ibi kan kì yóò bá wa.”

12Nítorí náà, nítorí tiyín,

ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,

Jerusalẹmu yóò sì di ebè

àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

New International Version

Micah 3:1-12

Leaders and Prophets Rebuked

1Then I said,

“Listen, you leaders of Jacob,

you rulers of Israel.

Should you not embrace justice,

2you who hate good and love evil;

who tear the skin from my people

and the flesh from their bones;

3who eat my people’s flesh,

strip off their skin

and break their bones in pieces;

who chop them up like meat for the pan,

like flesh for the pot?”

4Then they will cry out to the Lord,

but he will not answer them.

At that time he will hide his face from them

because of the evil they have done.

5This is what the Lord says:

“As for the prophets

who lead my people astray,

they proclaim ‘peace’

if they have something to eat,

but prepare to wage war against anyone

who refuses to feed them.

6Therefore night will come over you, without visions,

and darkness, without divination.

The sun will set for the prophets,

and the day will go dark for them.

7The seers will be ashamed

and the diviners disgraced.

They will all cover their faces

because there is no answer from God.”

8But as for me, I am filled with power,

with the Spirit of the Lord,

and with justice and might,

to declare to Jacob his transgression,

to Israel his sin.

9Hear this, you leaders of Jacob,

you rulers of Israel,

who despise justice

and distort all that is right;

10who build Zion with bloodshed,

and Jerusalem with wickedness.

11Her leaders judge for a bribe,

her priests teach for a price,

and her prophets tell fortunes for money.

Yet they look for the Lord’s support and say,

“Is not the Lord among us?

No disaster will come upon us.”

12Therefore because of you,

Zion will be plowed like a field,

Jerusalem will become a heap of rubble,

the temple hill a mound overgrown with thickets.