Mika 1 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 1:1-16

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

2Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,

fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,

1.2: 1Ọb 22.28.Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

3Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;

yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,

àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,

bí idà níwájú iná,

bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

5Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,

àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.

Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?

Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?

Kí ni àwọn ibi gíga Juda?

Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

6“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,

bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.

Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.

Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́

gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.

Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,

gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

8Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,

èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:

èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò

Èmi yóò ké bí akátá,

èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;

ó sì ti wá sí Juda.

Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,

àní sí Jerusalẹmu.

10Ẹ má ṣe sọ ní Gati

ẹ má ṣe sọkún rárá.

Ní ilẹ̀ Beti-Ofra

mo yí ara mi nínú eruku.

11Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,

ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.

Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani

kì yóò sì jáde wá.

Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;

A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,

Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.

13Ìwọ olùgbé Lakiṣi,

dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.

Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀

sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,

nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.

14Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀

fún Moreṣeti Gati.

Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.

15Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.

Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli

yóò sì wá sí Adullamu.

16Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀

nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,

sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,

nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

O Livro

Miqueias 1:1-16

1Estas são as mensagens que, da parte do Senhor, foram comunicadas a Miqueias, o morastita, durante os reinados de Jotão, Acaz e Ezequias, reis de Judá. Estas palavras dirigem-se a Samaria e a Judá. Miqueias recebeu-as na forma de visões.

Julgamento contra Samaria e Judá

2Prestem atenção! Que todos os povos do mundo ouçam! O Senhor Deus no seu santo templo tem acusações contra vocês!

3O Senhor está a chegar! Está a deixar o seu trono no céu e vem até à Terra, andando no cimo dos montes. 4Estes derretem-se sob os seus pés e escorrem em direção aos vales, como cera ante o fogo, como água jorrando duma encosta.

5Por que razão está isto a acontecer? Por causa dos pecados de Jacob e de Israel. Qual é o pecado de Jacob? Porventura não é Samaria? Qual é o altar idólatra de Judá? Não será Jerusalém?

6“Por isso, farei da cidade de Samaria um montão de ruínas. Será transformada num campo aberto; as suas ruas serão lavradas para se plantarem vinhas. Eu deitarei abaixo as muralhas, deixando os alicerces a descoberto; os blocos de pedra dessas construções rolarão até aos vales em baixo. 7Todas as imagens esculpidas que ali havia serão feitas em mil pedaços; os templos da idolatria, belamente decorados, erguidos com o dinheiro pago a prostitutas, também em templos de prostituição se tornarão.”

O lamento de Miqueias

8Por isso, levanto este lamento que é semelhante ao uivo dum chacal, ao grito duma coruja do deserto, atravessando as areias dum deserto de noite. Andarei despido e descalço, na tristeza e na vergonha. 9Porque a ferida do meu povo é demasiado profunda para se curar; estendeu-se por Judá; chegou até à porta de Jerusalém. 10Não o declarem em Gate! Não chorem! Em Bete-Le-Afra revolve-te no pó com angústia e vergonha. 11Ali vão os moradores de Safir, levados como escravos, desamparados, nus, envergonhados. O povo de Zaanãa nem ousa sequer mostrar-se fora das suas muralhas. Os alicerces de Bete-Ezel foram descobertos e desapareceram; eram os únicos fundamentos sobre os quais se mantinha. 12O povo de Marote em vão esperou por melhores dias; mas é só a amargura que os espera, enquanto o Senhor se mantiver contra Jerusalém.

13Depressa! Preparem já os vossos carros mais rápidos e fujam neles, ó povo de Laquis! Porque vocês foram os primeiros, de todas as cidades de Sião, a seguir Israel no seu pecado de idolatria. Todas as outras cidades do sul foram depois atrás do vosso exemplo.

14Por isso, darás presentes de despedida a Moresete de Gate; não há esperança de salvação para eles. A cidade de Aczibe enganou os reis de Israel, pois prometeu uma ajuda que não pode dar. 15Vocês, gente de Maressa, tornar-se-ão um prémio para aqueles que vos tomarem. Aquele que é a glória de Israel virá até Adulão.

16Chorem, chorem pelas vossas criancinhas! Rapem os cabelos até ficarem calvos como a águia! Rapem as vossas cabeças em sinal de pesar, porque os vossos filhos foram levados para o exílio!