Mika 1 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 1:1-16

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

2Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,

fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,

1.2: 1Ọb 22.28.Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

3Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;

yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,

àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,

bí idà níwájú iná,

bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

5Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,

àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.

Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?

Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?

Kí ni àwọn ibi gíga Juda?

Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

6“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,

bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.

Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.

Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́

gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.

Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,

gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

8Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,

èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:

èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò

Èmi yóò ké bí akátá,

èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;

ó sì ti wá sí Juda.

Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,

àní sí Jerusalẹmu.

10Ẹ má ṣe sọ ní Gati

ẹ má ṣe sọkún rárá.

Ní ilẹ̀ Beti-Ofra

mo yí ara mi nínú eruku.

11Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,

ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.

Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani

kì yóò sì jáde wá.

Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;

A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,

Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.

13Ìwọ olùgbé Lakiṣi,

dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.

Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀

sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,

nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.

14Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀

fún Moreṣeti Gati.

Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.

15Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.

Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli

yóò sì wá sí Adullamu.

16Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀

nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,

sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,

nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

New International Reader’s Version

Micah 1:1-16

1A message from the Lord came to Micah. He was from the town of Moresheth. The message came while Jotham, Ahaz and Hezekiah were kings of Judah. This is the vision Micah saw concerning Samaria and Jerusalem. Here is what he said.

2Listen to me, all you nations!

Earth and everyone who lives in it, pay attention!

The Lord and King will be a witness against you.

The Lord will speak from his holy temple in heaven.

The Lord Will Judge Samaria and Jerusalem

3The Lord is about to come down

from his home in heaven.

He rules over even the highest places on earth.

4The mountains will melt under him

like wax near a fire.

The valleys will be broken apart

by water rushing down a slope.

5All this will happen because

Jacob’s people have done what is wrong.

The people of Israel

have committed many sins.

Who is to blame

for the wrong things Jacob has done?

Samaria!

Who is to blame for the high places

where Judah’s people worship other gods?

Jerusalem!

6So the Lord says,

“I will turn Samaria into a pile of trash.

It will become a place for planting vineyards.

I will dump its stones down into the valley.

And I will destroy it

down to its very foundations.

7All the statues of Samaria’s gods

will be broken to pieces.

All the gifts its people gave to temple prostitutes

will be burned with fire.

I will destroy all the statues of its gods.

Samaria collected gifts that were paid to temple prostitutes.

So the Assyrians will use the gifts

to pay their own temple prostitutes.”

Micah Weeps Over His People

8I will weep and mourn because Samaria will be destroyed.

I’ll walk around barefoot and naked.

I’ll bark like a wild dog.

I’ll hoot like an owl.

9Samaria’s plague can’t be healed.

The plague has spread to Judah.

It has spread right up to the gate of my people.

It has spread to Jerusalem itself.

10Don’t tell the people of Gath about it.

Don’t let them see you weep.

People in Beth Ophrah, roll in the dust.

11You who live in the town of Shaphir,

leave naked and in shame.

Those who live in Zaanan

won’t come out to help you.

The people in Beth Ezel will mourn.

They won’t be able to help keep you safe any longer.

12Those who live in Maroth will groan with pain

as they wait for help.

That’s because the Lord will bring trouble on them.

It will reach the very gate of Jerusalem.

13You who live in Lachish,

get your fast horses ready to pull their chariots.

You trust in military power.

Lachish was where sin began

for the people of Zion.

The wrong things Israel did

were also done by you.

14People of Judah, you might as well say goodbye

to Moresheth near Gath.

The town of Akzib won’t give any help

to the kings of Israel.

15An enemy will attack

you who live in Mareshah.

Israel’s nobles will have to run away

and hide in the cave of Adullam.

16The children you enjoy so much

will be taken away as prisoners.

So shave your heads and mourn.

Make them as bare as the head of a vulture.