Mika 1 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Mika 1:1-16

1Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

2Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,

fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,

Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,

1.2: 1Ọb 22.28.Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

3Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;

yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,

àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,

bí idà níwájú iná,

bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

5Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,

àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.

Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?

Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?

Kí ni àwọn ibi gíga Juda?

Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

6“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,

bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.

Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.

Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́

gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:

Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.

Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,

gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

8Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,

èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:

èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò

Èmi yóò ké bí akátá,

èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;

ó sì ti wá sí Juda.

Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,

àní sí Jerusalẹmu.

10Ẹ má ṣe sọ ní Gati

ẹ má ṣe sọkún rárá.

Ní ilẹ̀ Beti-Ofra

mo yí ara mi nínú eruku.

11Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,

ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.

Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani

kì yóò sì jáde wá.

Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;

A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,

Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.

13Ìwọ olùgbé Lakiṣi,

dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.

Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀

sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,

nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.

14Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀

fún Moreṣeti Gati.

Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.

15Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.

Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli

yóò sì wá sí Adullamu.

16Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀

nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,

sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,

nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Miqueas 1:1-16

1Esta es la palabra que el Señor dirigió a Miqueas de Moréset, durante los reinados de Jotán, Acaz y Ezequías, reyes de Judá. Esta es la visión que tuvo acerca de Samaria y de Jerusalén.

La venida del Señor

2Escuchad, pueblos todos;

presten atención la tierra

y todo lo que hay en ella.

Desde su santo templo

el Señor, el Señor omnipotente,

será testigo contra vosotros.

3¡Mirad! Ya sale el Señor de su morada;

ya baja y se encamina

hacia las cumbres de la tierra.

4A su paso se derriten las montañas

como la cera junto al fuego;

se parten en dos los valles

como partidos por el agua de un torrente.

5Y todo esto por la transgresión de Jacob,

por los pecados del pueblo de Israel.

¿Acaso no representa Samaria

la transgresión de Jacob?

¿Y no es acaso en Jerusalén

donde están los santuarios paganos de Judá?

6Dejaré Samaria hecha un montón de ruinas:

¡convertida en campo arado para viñedos!

Arrojaré sus piedras al valle,

y pondré al descubierto sus cimientos.

7Todos sus ídolos serán hechos pedazos;

toda su paga de prostituta será arrojada al fuego.

Yo destrozaré todas sus imágenes.

Todo cuanto ganó como prostituta,

en paga de prostituta se convertirá.

Lamento de Miqueas

8Por eso lloraré y gritaré de dolor,

y andaré descalzo y desnudo.

Aullaré como chacal

y gemiré como avestruz.

9Porque la herida de Samaria es incurable:

ha llegado hasta Judá.

Se ha extendido hasta mi pueblo,

¡hasta la entrada misma de Jerusalén!

10No lo anunciéis en Gat,1:10 En hebreo, Gat suena como el verbo que significa anunciéis.

no os entreguéis al llanto;

¡revolcaos de dolor

en el polvo de Bet Leafrá!1:10 En hebreo, Bet Leafrá significa casa de polvo.

11Habitantes de Safir,1:11 En hebreo, Safir significa placentero.

emigrad desnudos y humillados.

Los habitantes de Zanán1:11 En hebreo, Zanán suena como el verbo que significa salir.

no se atrevieron a salir.

Bet Ésel está gimiendo,

y va a retirarles su apoyo.

12Se retuercen esperando el bien,

los habitantes de Marot;1:12 En hebreo, Marot suena como la palabra que significa amargura.

el Señor ha enviado el mal

hasta la entrada misma de Jerusalén.

13Habitantes de Laquis,1:13 En hebreo, Laquis suena como la palabra que significa corceles.

¡enganchad al carro los corceles!

Con vosotros comenzó el pecado de la hija de Sión;

en vosotros se hallaron los delitos de Israel.

14Por tanto, despedíos de Moréset Gat.

Los edificios de la ciudad de Aczib1:14 En hebreo, Aczib significa destrucción.

son una trampa para los reyes de Israel.

15Habitantes de Maresá,1:15 En hebreo, Maresá suena como la palabra que significa conquistador.

yo enviaré contra vosotros un conquistador,

y hasta Adulán irá a parar

la flor y nata de Israel.

16Así que rasúrate la barba y rápate la cabeza;

haz duelo por tus amados hijos;

agranda tu calva como la del buitre,

pues tus hijos te serán arrebatados.