Marku 1 – YCB & SNC

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Marku 1:1-45

Johanu onítẹ̀bọmi tún ọ̀nà ṣe sílẹ̀

1Ìbẹ̀rẹ̀ ìhìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.

21.2-8: Mt 3.1-12; Lk 3.2-16; Jh 1.6,15,19-28.1.2: Ml 3.1; Mt 11.10; Lk 7.27.Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé:

“Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ,

Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”

31.3: Isa 40.3.“Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù,

‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe,

ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’ ”

41.4: Ap 13.24.Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀. 5Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn. 6Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀. 7Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú. 8Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”

Ìtẹ̀bọmi àti ìdánwò Jesu

91.9-11: Mt 3.13-17; Lk 3.21-22; Jh 1.29-34.Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani. 10Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí. 111.11: Sm 2.7. Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”

121.12-13: Mt 4.1-11; Lk 4.1-13.Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù, 13Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.

Pípe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àkọ́kọ́

141.14-15: Mt 4.12-17; Lk 4.14-15.Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìhìnrere ti ìjọba Ọlọ́run. 15Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìhìnrere yìí gbọ́.”

161.16-20: Mt 4.18-22; Lk 5.1-11; Jh 1.40-42.Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n. 17Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.” 18Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.

19Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe. 20Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.

Jesu lé ẹ̀mí àìmọ́ jáde

211.21-22: Mt 7.28-29; Lk 4.31-32.Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni. 22Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn. 231.23-28: Lk 4.33-37.Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé, 241.24: Jh 6.69.“Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”

25Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.” 26Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.

27Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.” 28Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.

Jesu mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá

291.29-31: Mt 8.14-15; Lk 4.38-39.Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu. 30Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀. 31Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.

321.32-34: Mt 8.16-17; Lk 4.40-41.Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá. 33Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà. 34Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde, Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.

Jesu ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ láti gbàdúrà

351.35-38: Lk 4.42-43.Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà. 36Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a. 37Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”

38Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.” 391.39: Mt 4.23-25; Lk 4.44.Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.

Ọkùnrin tí o ní ààrùn ẹ̀tẹ̀

401.40-45: Mt 8.2-4; Lk 5.12-16.Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”

41Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.” 42Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.

43Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi 441.44: Le 13.49; 14.2-32.Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.” 45Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.

Slovo na cestu

Marek 1:1-45

Jan Křtitel připravuje cestu Ježíšovi

1Zde začíná radostná zpráva o podivuhodném životě Ježíše Krista, Božího Syna.

2Již prostřednictvím dávného proroka Izajáše Bůh promluvil tak, jako by mluvil přímo ke svému Synovi:

„Pošlu před tebou zvláštního posla,

který připraví svět na tvůj příchod.

3V době duchovně pusté bude volat:

‚Přichází k vám Bůh!

Napravte svůj život,

odložte všechno,

co mu stojí v cestě!‘ “

4Tím poslem byl Jan Křtitel. Žil na poušti a vybízel lidi, aby od něho přijali křest a dali tak najevo, že se veřejně přiznávají ke svým proviněním, že jich litují a touží, aby jim Bůh odpustil. 5Lidé z Jeruzaléma a z celého Judska přicházeli, aby mu naslouchali, a když vyznali své viny, Jan je pokřtil v řece Jordánu. 6Jan nosil oděv z velbloudí srsti přepásaný pásem a živil se kobylkami a medem divokých včel. 7Ve svých kázáních stále zdůraz-ňoval:

„Záhy po mně přijde někdo daleko mocnější, než jsem já; bude tak vznešený, že nejsem hoden ani jako otrok rozvázat řemínek jeho obuvi.

8Já jsem vás křtil vodou, ale on vás bude křtít Duchem svatým.“

Jan křtí Ježíše

9Jednoho dne přišel Ježíš z galilejského Nazaretu k Janovi a dal se od něho v Jordánu pokřtít. 10Ve chvíli, kdy vystupoval z vody na břeh, viděl, jak se obloha rozevřela a na jeho hlavu se snesl Boží Duch v podobě holubice. 11Současně z nebe promluvil hlas: „Ty jsi můj milovaný Syn, z tebe mám radost.“

Satan pokouší Ježíše na poušti

12Hned nato Boží Duch vnukl Ježíšovi, aby odešel na poušť do samoty. 13Šel tedy a čtyřicet dní tam strávil sám mezi divokou zvěří, vystaven satanovu pokoušení; potom přišli andělé a pečovali o něho.

Ježíš káže v Galileji

14Později, když král Herodes uvěznil Jana Křtitele, vydal se Ježíš do Galileje a hlásal tam radostné poselství od Boha: 15„Konečně přišel čas a přiblížilo se Boží království. Přestaňte myslet jen na pozemské věci, změňte svůj život a uvěřte tomu, co vám Bůh vzkazuje!“

Čtyři rybáři následují Ježíše

16Jednoho dne šel Ježíš po břehu Galilejského jezera a uviděl Šimona a jeho bratra Ondřeje, jak vrhají do vody síť; byli totiž rybáři.

17Ježíš na ně zavolal: „Pojďte za mnou! Udělám z vás jiné rybáře, budete lovit lidi!“ 18Ti dva všeho nechali a šli s ním.

19O něco dále pak spatřil jiné dva rybáře – Jakuba a Jana Zebedeovy. Seděli v lodi a opravovali potrhané sítě. 20I ty Ježíš vyzval. Oba bratři se okamžitě zvedli, opustili svého otce a najaté pomocníky a vykročili za Ježíšem.

Ježíš učí jako ten, kdo má moc

21Tak přišli společně do města jménem Kafarnaum; v sobotu navštívili tamější synagogu, ve které se židé scházeli ke společným modlitbám, ke čtení i výkladu Písma. Ježíš tam začal kázat a 22posluchači žasli, protože mluvil s nezvyklou přesvědčivostí. Bylo to úplně něco jiného, než co dosud slýchali od učitelů zákona.

23Byl tam také jeden muž posedlý démonem a ten začal vykřikovat: 24„Co je ti po nás, Ježíši Nazaretský? Chceš nás snad zničit? Vím dobře, že jsi svatý Boží Syn!“

25Ježíš ho rázně okřikl: „Už ani slovo! Vyjdi z něho ven!“ 26Posedlý se ještě chvíli zmítal a křičel, než ho démon opustil.

27Lidé byli ohromeni a začali se dohadovat: „Co to je? Nové učení? Odkud bere takovou moc? Vždyť i zlým duchům poroučí a oni ho poslouchají!“

28A zpráva o tom, co Ježíš učinil, se rychle roznesla po celém kraji.

Ježíš uzdravuje Petrovu tchyni a mnoho dalších

29Když pak Ježíš opustil synagogu, vydal se s Jakubem a Janem do Šimonova a Ondřejova domu. 30Šimonova tchyně právě ležela v horečkách na lůžku, tak o tom pověděli Ježíšovi. 31Ten k ní přistoupil, vzal ji za ruku a pomohl jí, aby si sedla. Horečka hned přestala, žena vstala a začala se starat o hosty.

32-33Jakmile slunce zmizelo za obzorem (a skončil sobotní klid), sešli se lidé z celého města u Šimonova domu. Přivedli s sebou nemocné a posedlé. 34Toho večera uzdravil Ježíš mnoho lidí a z velkého množství posedlých vyhnal démony. Těm však nedovolil mluvit, protože věděli, že je Mesiáš – svatý Boží Syn.

Ježíš káže a uzdravuje

35Příští ráno vstal Ježíš ještě před svítáním a odešel na osamělé místo, kde se mohl v klidu modlit.

36O něco později jej Šimon se svými druhy začali hledat. 37Když ho našli, řekli mu: „Každý se ptá jenom po tobě!“

38Ježíš jim však pověděl: „Musím jít také do jiných měst, abych i tam oznámil své poselství. Vždyť proto jsem přišel.“

39A tak procházel celou galilejskou zemí, kázal v synagogách a mnohé vysvobozoval z moci démonů.

Ježíš uzdravuje malomocného

40Jednou za ním přišel člověk postižený malomocenstvím a na kolenou ho prosil: „Pane, vím, že mne můžeš uzdravit, když budeš chtít.“

41Ježíš, pohnut soucitem, vztáhl ruku, dotkl se ho a řekl: „Chci, abys byl zdráv.“ 42V tu chvíli malomocenství zmizelo a muž byl uzdraven.

43-44Ježíš mu však přísně nařídil: „Jdi a dej si své uzdravení ověřit knězem. Cestou se však nikde nezastavuj a s nikým nemluv. Vezmi s sebou obětní dar, jak to uzdraveným z malomocenství předepsal Mojžíš, aby se všichni přesvědčili, že jsi očištěn.“

45Muž odešel, ale nevydržel mlčet. Každému na potkání radostně vyprávěl, že je uzdraven. A tak Ježíš nemohl veřejně vstoupit do žádného města a zůstával venku na osamělých místech. I tam se však za ním ze všech stran táhly zástupy lidí.