Malaki 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Malaki 1:1-14

1Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.

Ọlọ́run fẹ́ràn Jakọbu, o sì kórìíra Esau

21.2-3: Ro 9.13.1.2-5: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ọd.“Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’

“Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu, 3ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”

4Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.”

Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa. 5Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’

Ẹbọ àìmọ́

6“Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’

7“Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi.

“Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’

“Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn. 8Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

9“Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

10“Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín. 11Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

12“Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn. 13Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí. 14“Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

Nouă Traducere În Limba Română

Maleahi 1:1-14

1O rostire a Cuvântului Domnului către Israel prin Maleahi.1 Sau: prin mesagerul Meu.

Întâietatea lui Iacov

2„V‑am iubit! zice Domnul. Dar voi spuneți: «Cum ne‑ai iubit?» N‑a fost Esau fratele lui Iacov? zice Domnul. Și totuși pe Iacov l‑am iubit, 3dar pe Esau l‑am urât. I‑am prefăcut munții într‑o pustietate, iar moștenirea lui am dat‑o șacalilor din pustie.“ 4Dacă Edom ar zice: „Suntem doborâți, dar ne vom întoarce și vom rezidi ruinele!“, atunci așa vorbește Domnul Oștirilor4 Ebr.: YHWH Țebaot. Termenul ebraic pentru oștiri se poate referi la: (1) oștirile lui Israel (Ex. 7:4; Ps. 44:9); (2) corpurile cerești (Gen. 2:1; Deut. 4:19; Is. 40:26); (3) îngeri (Ios. 5:14; 1 Regi 22:19; Ps. 148:2). Acest titlu face referire, probabil, la suveranitatea lui Dumnezeu peste orice putere din univers [peste tot în carte].: „Ce vor rezidi ei, voi dărâma Eu. Și vor fi numiți: «Teritoriul Răutății, Poporul pe care Domnul este indignat pentru totdeauna». 5Veți vedea lucrul acesta cu ochii voștri și veți zice: «Mărit să fie Domnul dincolo de hotarele lui Israel!»

Necredincioșia lui Israel

(1:6–2:16)

Un cuvânt de mustrare pentru preoți

6Un fiu îl cinstește pe tatăl său și un rob îi dă cinste stăpânului său. Dacă sunt Tată, unde este cinstea care Mi se cuvine? Și dacă sunt Stăpân, unde este teama față de Mine? vă spune Domnul Oștirilor vouă, preoților, care disprețuiți Numele Meu. Voi însă spuneți: «Cum Ți‑am disprețuit noi Numele?» 7Aducând pe altarul Meu hrană pângărită. Dar voi spuneți: «Cum Te‑am pângărit?» Spunând că masa Domnului este de disprețuit7 În sensul că nu contează ce fel de jertfă este adusă pe altar (vezi prima parte a v. 7).. 8Când aduceți ca jertfă animale oarbe, nu este acesta un lucru rău? Iar când aduceți animale șchioape sau bolnave, nu este acesta un lucru rău?8 Vezi Lev. 22:17-25. Încearcă să le aduci guvernatorului tău! Va fi el oare mulțumit de tine? Te va lua el în seamă? zice Domnul Oștirilor.

9Și acum, căutați fața lui Dumnezeu ca să‑Și arate bunăvoința față de noi. Vă va lua El în seamă de vreme ce mâinile voastre aduc astfel de daruri?9 Sau: noi! Vina este a voastră! Vă va lua El în seamă?, zice Domnul Oștirilor.

10O, de ar închide careva dintre voi porțile Templului, ca să nu mai aprindeți degeaba focul pe altarul Meu! Nu‑Mi găsesc nicio plăcere în voi, zice Domnul Oștirilor, și nu voi accepta niciun dar de mâncare din mâinile voastre. 11Căci de la răsăritul soarelui și până la asfințitul lui11 Sau: de la un capăt al pământului și până la celălalt. Numele Meu este mare printre neamuri. Și în orice loc se arde tămâie în cinstea Numelui Meu, și se aduc daruri de mâncare curate, căci Numele Meu este11 Verbele din acest verset pot fi redate și la timpul viitor: va fi, se va arde, se vor aduce, va fi, în TM verbul fiind fie omis, fie la modul participiu. mare printre neamuri, zice Domnul Oștirilor.

12Dar voi Îl batjocoriți, zicând: «Masa Domnului este pângărită și rodul ei este o hrană de disprețuit!12 Sau: Masa Domnului poate fi pângărită și rodul ei poate fi o hrană de disprețuit!» 13Voi ziceți: «Iată, ce osteneală!» și vă strâmbați la ea13 Sau: la El., zice Domnul Oștirilor. Apoi aduceți ce a fost luat prin jaf, ce este șchiop sau bolnav. Da, astfel de daruri de mâncare aduceți! Să le primesc Eu din mâinile voastre? zice Domnul. 14Blestemat să fie înșelătorul care are în turma sa un mascul sănătos și care, deși jură că‑l va aduce pe acesta, totuși îl jertfește Domnului pe cel cu meteahnă. Căci Eu sunt un Împărat mare, zice Domnul Oștirilor, și Numele Meu este de temut printre neamuri.