Kolose 1 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Kolose 1:1-29

1Paulu, aposteli Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti Timotiu arákùnrin wa.

21.2: Ro 1.7.Sí àwọn ẹni mímọ́ àti àwọn arákùnrin àti arábìnrin nínú Kristi tí wọ́n ń gbé ní ìlú Kolose.

Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún un yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa.

Àwọn ọpẹ́ àti àdúrà

31.3: Ef 1.16.Nígbàkúgbà tí a bá ń gbàdúrà fún un yín ni a máa ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run Baba Olúwa wa Jesu Kristi. 4Nítorí a ti gbúròó ìgbàgbọ́ yín nínú Jesu Kristi, àti bí ẹ ti ṣe fẹ́ràn gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́. 5Ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ tí ń sàn nínú ìrètí tí a gbé pamọ́ fún un yín ní ọ̀run èyí tí ẹ̀yin sì ti gbọ́ tẹ́lẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́ ìhìnrere náà, 6èyí tí ó ti dé ọ̀dọ̀ yín. Káàkiri àgbáyé ni ìhìnrere yìí ń so èso tí ó sì ń dàgbà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń ṣe láàrín yín láti ọjọ́ náà tí ẹ ti gbọ́ ọ, tí ẹ sì ní ìmọ̀ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run nínú gbogbo òtítọ́ rẹ̀. 71.7: Kl 4.12; Fm 23.Ẹ̀yin ti kọ́ ọ lọ́dọ̀ Epafira, ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ wa olùfẹ́, ẹni tí ó jẹ́ olóòtítọ́ ìránṣẹ́ Kristi ní ipò wa. 8Ẹni ti ó sọ fún wa nípa ìfẹ́ yín nínú ẹ̀mí.

91.9: Ef 1.15-17.Nítorí ìdí èyí, láti ọjọ́ tí a ti gbọ́ nípa yín, a kò sinmi láti máa gbàdúrà fún yin, tí a sì ń gbàdúrà pé kí Ọlọ́run fi ìmọ̀ ìfẹ́ rẹ̀ kún yín nípasẹ̀ ọgbọ́n àti òye gbogbo tí ń ṣe ti Ẹ̀mí. 10Àwa sì ń gbàdúrà yìí kí ẹ lè gbé irú ìgbé ayé tó yẹ fún Olúwa kí ẹ sì máa wu ú ní gbogbo ọ̀nà, kí ẹ sì máa so èso rere gbogbo, kí ẹ sì máa dàgbà nínú ìmọ̀ Ọlọ́run, 11pé kí a lè fi ipa gbogbo sọ yín di alágbára gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ àti ògo rẹ̀, kí ó lè ṣe é ṣe fún un yín láti máa tẹ̀síwájú nínú sùúrù àti ìpamọ́ra pẹ̀lú ayọ̀. 12Kí a máa dúpẹ́ nígbà gbogbo lọ́wọ́ Baba, ẹni tí ó kà yín láti jẹ́ alábápín nínú ogún àwọn ẹni mímọ́ nínú ìjọba ìmọ́lẹ̀. 131.13: Ef 1.21; 2.2.Nítorí tí ó ti já wa gbà kúrò nínú agbára òkùnkùn ó sì mú wa wá sí ìjọba Ọmọ tí ó fẹ́ràn. 14Nínú ẹni tí a ní ìràpadà, àti ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.

Títóbi Kristi

151.15: 2Kọ 4.4.Kristi ni àwòrán Ọlọ́run tí a kò le rí, àkọ́bí gbogbo ẹ̀dá. 16Nítorí nípa rẹ̀ ní a dá ohun gbogbo: àwọn ohun tí ń bẹ ní ọ̀run àti ní ayé, ohun tí a rí àti èyí tí a kò rí, wọn ìbá ṣe ìtẹ́, tàbí agbára, tàbí àṣẹ, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo àti fún un. 171.17: Òw 8.22-31.Ó ti wà ṣáájú kí ohunkóhun tó wà, nínú rẹ̀ ni a sì so ohun gbogbo papọ̀ ṣọ̀kan. 181.18: Ef 4.15.Òun ni orí fún ara, èyí tí í ṣe ìjọ; òun ni ìbẹ̀rẹ̀ àti àkọ́bí nínú àwọn òkú, pé nínú ohun gbogbo kí òun lè ní ipò tí ó ga jùlọ nínú ohunkóhun. 19Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí gbogbo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òun tìkára rẹ̀ lè máa gbé nínú rẹ̀. 20Àti nípasẹ̀ rẹ̀ láti bá ohun gbogbo làjà àwọn nǹkan tí ń bẹ láyé àti èyí tí ń bẹ ní ọ̀run, nípa mímú àlàáfíà wá nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, tí a ta sílẹ̀ lórí igi àgbélébùú.

21Ẹ̀yin ya ara yín nípá kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà kan rí, ẹ jẹ́ ọ̀tá nínú ọkàn yín nítorí ìwà búburú yín. 22Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti bá yín làjà nípa ara Kristi nípa ikú láti mú un yín lọ sí iwájú rẹ̀ ní mímọ́, aláìlábàwọ́n àti kúrò nínú ìdálẹ́bi, 23bí ẹ̀yin bá dúró nínú ìgbàgbọ́ yín, tí ẹ fi ẹsẹ̀ múlẹ̀, tí ẹ sì dúró ṣinṣin, láláìyẹsẹ̀ kúrò nínú ìrètí ti ìhìnrere ti ẹ̀yin ti gbọ́, èyí tí a ti wàásù rẹ̀ fún gbogbo ẹ̀dá lábẹ́ ọ̀run, àti èyí ti èmi Paulu ṣe ìránṣẹ́ fún.

Iṣẹ́ Paulu ṣíṣe fún àwọn ìjọ

24Nísinsin yìí èmi ń yọ̀ nínú ìjìyà fún un yín. Inú mi sì dùn, nítorí mo ń ṣe ìrànlọ́wọ́ láti jẹ ìyà tó ṣẹ́kù nínú ìyà Kristi fún ara rẹ̀, èyí tí ì ṣe ìjọ. 251.25: Ef 3.2.Nínú èyí tí a fi ṣe ìránṣẹ́ fún gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ìríjú Ọlọ́run tí a fi fún mi fún yín láti mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣẹ. 261.26: Ef 3.9.Ó ti pa àṣírí ìjìnlẹ̀ yìí mọ́ fún ayérayé àti láti ìrandíran. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀, ó ti fihàn fún àwọn ẹni mímọ́. 27Àwọn ẹni tí Ọlọ́run yàn láti fihàn láàrín àwọn aláìkọlà nípa ọ̀rọ̀ ògo ohun ìjìnlẹ̀ yìí, èyí tí í ṣe Kristi ìrètí ògo nínú yín.

28Àwa ń wàásù rẹ̀, a ń gbani níyànjú a sì ń kọ olúkúlùkù ènìyàn ní ọgbọ́n gbogbo, kí a lè mú olúkúlùkù dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní pípé nínú Kristi. 29Sí èyí sì ni èmi ń ṣe làálàá, ti mo sì ń làkàkà pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀, èyí tó ń ṣiṣẹ́ nínú mi.

Słowo Życia

Kolosan 1:1-29

Pozdrowienie

1Ja, Paweł, wybrany przez Boga na apostoła Chrystusa Jezusa, wraz z Tymoteuszem, uczniem Pana, 2piszę do wierzących w Kolosach—świętych i ufających Chrystusowi. Niech Bóg, nasz Ojciec, i Pan, Jezus Chrystus, obdarzają was swoją łaską i pokojem!

Podziękowanie i modlitwa

3Za każdym razem, gdy się za was modlimy, dziękujemy Bogu—Ojcu naszego Pana, Jezusa Chrystusa, za to, że was powołał. 4Słyszeliśmy bowiem, że szczerze wierzycie Chrystusowi Jezusowi i kochacie wszystkich wierzących. 5W niebie czeka was nagroda, o której dowiedzieliście się słuchając prawdziwej dobrej nowiny. 6Dotarła ona do was w taki sam sposób, w jaki dociera do ludzi na całym świecie, wszędzie przemieniając życie tych, którzy ją przyjmują. Tak samo było z wami, począwszy od dnia, w którym usłyszeliście i przyjęliście prawdę o Bożej łasce. 7Tym, który przyniósł wam dobrą nowinę, był nasz drogi współpracownik, Epafras. Jest on oddanym sługą Chrystusa 8i to on opowiedział nam o miłości, którą Duch Święty wlał w wasze serca.

9Dlatego od chwili, w której się o tym dowiedzieliśmy, nie przestajemy się za was modlić. Prosimy Boga, aby pomógł wam w pełni zrozumieć swoją wolę i by obdarzył was mądrością oraz duchowym rozeznaniem. 10Modlimy się również o to, abyście żyli w sposób oddający chwałę Panu i podobający się Mu, oraz aby wasze życie było pełne dobrych czynów i byście coraz lepiej poznawali Boga.

11Prosimy Boga także o to, abyście—napełnieni Jego potężną i wspaniałą mocą—byli coraz bardziej cierpliwi i wytrwali, i byście z radością 12okazywali wdzięczność Bogu Ojcu. To On sprawił bowiem, że razem z innymi świętymi, którzy żyją w Jego świetle, korzystacie z Jego daru. 13On wyrwał nas z królestwa ciemności i przeniósł do królestwa swojego ukochanego Syna, 14który zbawił nas i zapewnił przebaczenie grzechów.

Wyższość Chrystusa

15Chrystus jest widzialnym odbiciem niewidzialnego Boga i panuje nad całym światem. 16Przez Niego bowiem Bóg stworzył wszystko, co jest w niebie i na ziemi, zarówno to, co widoczne, jak i to, czego nie można zobaczyć. Jego dziełem są wszyscy władcy tego świata, a także wszelkie duchowe moce. Wszystko to zostało stworzone przez Niego i dla Niego. 17Zanim cokolwiek powstało, On już był. Wszystko istnieje dzięki Niemu.

18On jest Głową ciała, którym jest kościół. On jest również początkiem wszystkiego i pierwszym, który zmartwychwstał—w ten sposób dostąpił wywyższenia. 19Bóg zapragnął bowiem w pełni zamieszkać w swoim Synu 20i przez Niego pojednać ze sobą cały świat. Dzięki krwi Jezusa, przelanej na krzyżu, zapewnił On pokój całemu niebu i całej ziemi. 21Również was, którzy—z powodu złych czynów—niedawno jeszcze byliście dla Niego obcy i wrodzy, 22teraz pojednał ze sobą dzięki śmierci Jezusa. Pragnął bowiem, abyście byli święci, niewinni i bez zarzutu. 23Macie jednak nieustannie Mu wierzyć, budować wasze życie na solidnym fundamencie i nie dać się odciągnąć od nadziei, którą przynosi dobra nowina. Ona to jest głoszona na całym świecie, a ja, Paweł, poświęciłem jej życie.

Praca Pawła dla kościoła

24Pomimo cierpień, jakie za was znoszę, jestem pełen radości. Mam bowiem udział w cierpieniu Chrystusa za kościół, będący Jego ciałem. 25I służę kościołowi z polecenia samego Boga, głosząc wam jako Jego słowo 26tajemnicę, która była niedostępna przez wiele stuleci i pokoleń, ale teraz została ujawniona Jego świętym. 27Bóg postanowił bowiem objawić wam, poganom, jej wielkie bogactwo i chwałę. A tajemnicą tą jest Chrystus, który żyje w was i obdarza was nadzieją na przyszłą chwałę. 28To właśnie o Nim opowiadamy ludziom, ostrzegając ich i nauczając Bożej mądrości. Pragniemy bowiem, aby—dzięki Chrystusowi Jezusowi—każdy człowiek stał się doskonały. 29O to walczę i nad tym pracuję, a czynię to dzięki mocy otrzymanej od Boga.