Bilidadi
1Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé:
2“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó?
Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
3Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí?
Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
4Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i,
ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
5Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò,
tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
6Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin:
ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ,
òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
7Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í,
bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
8“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì
kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
9Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan,
nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
10Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ?
Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
11Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀
tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
12Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀,
ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀
13Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run,
bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
14Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò,
àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
15Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró,
yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
16Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn,
ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
17Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká,
ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
18Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀,
nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
19Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù
àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
20“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù,
bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
21títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu,
àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
22ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀,
àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”
بلدد سخن میگويد: ايوب بايد توبه كند
1آنگاه بلدد شوحی پاسخ داد:
2ای ايوب، تا به كی به اين حرفها ادامه میدهی؟ حرفهای تو باد هواست! 3آيا خدای قادر مطلق عدالت و انصاف را زير پا میگذارد؟ 4فرزندانت به خدا گناه كردند و او به حق، ايشان را مجازات نمود. 5ولی اكنون تو به درگاه خدای قادر مطلق دعا كن. 6اگر آدم پاک و خوبی باشی، او دعايت را میشنود و تو را اجابت میكند و خانهٔ تو را بركت میدهد. 7عاقبت تو آنچنان از خير و بركت سرشار خواهد شد كه زندگی گذشتهات در برابر آن ناچيز به نظر خواهد آمد.
8از سالخوردگان بپرس تا از تجربهٔ خود به تو بياموزند. 9ما آنقدر زندگی نكردهايم كه همه چيز را بدانيم. 10تو میتوانی از حكمت گذشتگان درس عبرت بگيری و آنها به تو خواهند گفت كه 11-13آنان كه خدا را فراموش میكنند ديگر اميدی ندارند. ايشان مانند گياهی در زمين بیآب هستند كه حتی پيش از آنكه آن را ببرند پژمرده میشود. 14شخص بیخدا مانند كسی است كه به تار عنكبوت اعتماد كند. 15اگر به آن تكيه نمايد، میافتد و اگر از آن آويزان شود، آن تار او را نگه نمیدارد. 16او مانند گياهی است كه صبحگاهان تر و تازه میشود و شاخههايش در باغ گسترده میگردند. 17در ميان سنگها ريشه میدواند و خود را محكم نگه میدارد. 18ولی وقتی آن را از ريشه میكنند ديگر كسی آن را به ياد نمیآورد، 19و گياهان ديگری روييده جای آن را میگيرند. چنين است عاقبت شخص بیخدا.
20ولی بدان كه خدا نيكان را ترک نمیگويد و بدكاران را كامياب نمیگرداند. 21او دهانت را از خنده و فريادهای شادی پر خواهد كرد، 22و دشمنانت را رسوا و خانهٔ بدكاران را خراب خواهد نمود.