Jobu 8 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 8:1-22

Bilidadi

1Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé:

2“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó?

Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?

3Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí?

Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?

4Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i,

ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.

5Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò,

tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.

6Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin:

ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ,

òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.

7Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í,

bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.

8“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì

kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.

9Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan,

nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.

10Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ?

Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?

11Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀

tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?

12Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀,

ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀

13Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run,

bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.

14Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò,

àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.

15Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró,

yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.

16Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn,

ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.

17Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká,

ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.

18Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀,

nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’

19Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù

àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.

20“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù,

bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́

21títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu,

àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,

22ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀,

àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”

Nueva Versión Internacional

Job 8:1-22

Primer discurso de Bildad

1A esto respondió Bildad de Súah:

2«¿Hasta cuándo seguirás hablando así?

¡Tus palabras son un viento huracanado!

3¿Acaso Dios pervierte la justicia?

¿Acaso tuerce el derecho el Todopoderoso?

4Si tus hijos pecaron contra Dios,

él les dio lo que su pecado merecía.

5Pero si tú buscas a Dios,

si diriges tu súplica al Todopoderoso,

6y si eres puro e intachable,

él saldrá en tu defensa8:6 saldrá en tu defensa. Alt. velará por ti.

y te restablecerá en el lugar que te corresponde.

7Modestas parecerán tus primeras riquezas,

comparadas con tu prosperidad futura.

8»Pregunta a las generaciones pasadas;

averigua lo que descubrieron sus antepasados.

9Nosotros nacimos ayer y nada sabemos;

nuestros días en este mundo son como una sombra.

10Pero ellos te instruirán, te lo harán saber;

compartirán contigo su experiencia.

11¿Puede crecer el papiro donde no hay pantano?

¿Pueden crecer los juncos donde no hay agua?

12Aunque estén floreciendo y nadie los haya cortado,

se marchitan antes que otra hierba.

13Tal es el destino de los que se olvidan de Dios;

así termina la esperanza de los impíos.

14Muy frágiles8:14 frágiles. Palabra de difícil traducción. son sus esperanzas;

han puesto su confianza en una telaraña.

15No podrán sostenerse cuando se apoyen en ella;

no quedarán en pie cuando se prendan de sus hilos.

16Son como plantas frondosas expuestas al sol,

que extienden sus ramas por todo el jardín:

17hunden sus raíces en torno a un montón de piedras

y buscan arraigarse entre ellas.

18Pero si las arrancan de su sitio,

ese lugar negará haberlas visto.

19¡Así termina su alegría de vivir

y del suelo brotan otras plantas!

20»Dios no rechaza a quien es íntegro

ni brinda su apoyo a quien hace el mal.

21Pondrá de nuevo risas en tu boca

y gritos de alegría en tus labios.

22Tus enemigos se cubrirán de vergüenza

y desaparecerán las moradas de los malvados».