Jobu 40 – YCB & AKCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 40:1-24

Jobu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀

1Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé:

2“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́?

Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”

3Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,

4“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà?

Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.

5Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́;

lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”

6Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé:

7“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin,

èmi ó bi ọ léèrè,

kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.

8“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán?

Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo

9Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run

tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?

10Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́,

tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.

11Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde;

kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.

12Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀

kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.

13Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀,

kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú

14Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé,

ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.

15“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti,

tí mo dá pẹ̀lú rẹ,

òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.

16Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,

àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.

17Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari;

Iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.

18Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ;

Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.

19Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run;

síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.

20Nítòótọ́ òkè ńláńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá,

níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.

21Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì,

lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.

22Igi lótusì ṣíji wọn bò o;

igi arọrọ odò yí i káàkiri.

23Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ;

ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.

24Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀,

tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

Akuapem Twi Contemporary Bible

Hiob 40:1-24

1Afei Awurade buaa Hiob se,

2“Nea ɔne Otumfo no wɔ asɛm no bɛteɛ ne so ana?

Ma nea ɔbɔ Onyankopɔn kwaadu no mmua no ɛ!”

3Na Hiob buaa Awurade se,

4“Mensɛ na memfata, ɛbɛyɛ dɛn na matumi anya mmuae?

Mede me nsa mua mʼano.

5Makasa baako, nanso minni mmuae

mprenu so, na merenkasa bio.”

6Afei, Awurade fi ahum mu buaa Hiob se,

7“Hyɛ wo ho den sɛ ɔbarima;

mebisa wo nsɛm,

na ɛsɛ sɛ wubua me.

8“Wobɛka mʼatemmu ho asɛm bɔne ana?

Wubebu me fɔ de abu wo ho bem ana?

9Wowɔ abasa te sɛ Onyankopɔn de,

na wo nne betumi abobɔ mu sɛ ne de ana?

10Ɛno de fa anuonyam ne ɔhyerɛn hyehyɛ wo ho,

na fura nidi ne kɛseyɛ.

11Hwie wʼabufuwhyew mmoroso no gu,

hwɛ ɔhantanni biara na brɛ no ase,

12hwɛ ɔhantanni biara na si no fam

na tiatia amumɔyɛfo so wɔ faako a wogyina hɔ.

13Sie wɔn nyinaa bɔ mu wɔ mfutuma mu;

kata wɔn anim wɔ ɔda mu.

14Na afei mʼankasa megye ato mu sɛ

wo ara wo basa nifa betumi agye wo nkwa.

15“Hwɛ susono,

nea meyɛɛ no kaa wo ho

na ɔwe sare te sɛ nantwi.

16Hwɛ ahoɔden a ɔwɔ wɔ nʼasen mu

ne ahoɔden a ɛwɔ ne yafunu so were mu!

17Ne dua hinhim sɛ sida;

ne srɛ mu ntin yɛ peperee.

18Ne nnompe te sɛ kɔbere mfrafrae dorobɛn,

nʼabasa ne ne nʼanan te sɛ nnade praban.

19Odi Onyankopɔn nsa ano adwuma mu kan,

nanso ne Yɛfo betumi de nʼafoa akɔ ne so.

20Nkoko fifi wɔn nnɔbae ma no,

na wuram mmoa nyinaa goru bɛn hɔ.

21Nsɔensɔe nnua ase na ɔda,

na dontori mu demmire akata no so.

22Nsɔensɔe nwini no kata ne so;

na nsunoa nnua twa ne ho hyia.

23Nsu nworoso nhaw no;

mpo sɛ Yordan bobɔ ba nʼano a, onni ɔhaw.

24Obi betumi akyere no animono;

anaa obi betumi de afiri ayi no na wabɔre ne hwene mu ana?