Jobu 4 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 4:1-21

Ọ̀rọ̀ Elifasi: Ọlọ́run kì í fi ìyà jẹ olódodo

1Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé:

2“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?

Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?

3Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,

ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.

4Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,

ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.

5Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́;

ara rẹ kò lélẹ̀.

6Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ

àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?

7“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí: Ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?

Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?

8Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,

tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.

9Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,

nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.

10Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún

àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.

11Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,

àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.

12“Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi,

etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.

13Ní ìrò inú lójú ìran òru,

nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.

14Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì

tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.

15Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi,

irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.

16Ó dúró jẹ́ẹ́,

ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,

àwòrán kan hàn níwájú mi,

ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:

17‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run,

ènìyàn ha le mọ́ ju Ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?

18Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.

19Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,

ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀

tí yóò di rírun kòkòrò.

20A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́

wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.

21A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí?

Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

New International Version

Job 4:1-21

Eliphaz

1Then Eliphaz the Temanite replied:

2“If someone ventures a word with you, will you be impatient?

But who can keep from speaking?

3Think how you have instructed many,

how you have strengthened feeble hands.

4Your words have supported those who stumbled;

you have strengthened faltering knees.

5But now trouble comes to you, and you are discouraged;

it strikes you, and you are dismayed.

6Should not your piety be your confidence

and your blameless ways your hope?

7“Consider now: Who, being innocent, has ever perished?

Where were the upright ever destroyed?

8As I have observed, those who plow evil

and those who sow trouble reap it.

9At the breath of God they perish;

at the blast of his anger they are no more.

10The lions may roar and growl,

yet the teeth of the great lions are broken.

11The lion perishes for lack of prey,

and the cubs of the lioness are scattered.

12“A word was secretly brought to me,

my ears caught a whisper of it.

13Amid disquieting dreams in the night,

when deep sleep falls on people,

14fear and trembling seized me

and made all my bones shake.

15A spirit glided past my face,

and the hair on my body stood on end.

16It stopped,

but I could not tell what it was.

A form stood before my eyes,

and I heard a hushed voice:

17‘Can a mortal be more righteous than God?

Can even a strong man be more pure than his Maker?

18If God places no trust in his servants,

if he charges his angels with error,

19how much more those who live in houses of clay,

whose foundations are in the dust,

who are crushed more readily than a moth!

20Between dawn and dusk they are broken to pieces;

unnoticed, they perish forever.

21Are not the cords of their tent pulled up,

so that they die without wisdom?’