Jobu 4 – YCB & KJV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 4:1-21

Ọ̀rọ̀ Elifasi: Ọlọ́run kì í fi ìyà jẹ olódodo

1Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé:

2“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?

Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?

3Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,

ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.

4Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,

ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.

5Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́;

ara rẹ kò lélẹ̀.

6Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ

àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?

7“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí: Ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?

Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?

8Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,

tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.

9Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,

nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.

10Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún

àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.

11Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,

àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.

12“Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi,

etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.

13Ní ìrò inú lójú ìran òru,

nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.

14Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì

tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.

15Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi,

irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.

16Ó dúró jẹ́ẹ́,

ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,

àwòrán kan hàn níwájú mi,

ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:

17‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run,

ènìyàn ha le mọ́ ju Ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?

18Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.

19Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,

ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀

tí yóò di rírun kòkòrò.

20A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́

wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.

21A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí?

Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

King James Version

Job 4:1-21

1Then Eliphaz the Temanite answered and said, 2If we assay to commune with thee, wilt thou be grieved? but who can withhold himself from speaking?4.2 to…: Heb. a word4.2 withhold…: Heb. refrain from words? 3Behold, thou hast instructed many, and thou hast strengthened the weak hands. 4Thy words have upholden him that was falling, and thou hast strengthened the feeble knees. 5But now it is come upon thee, and thou faintest; it toucheth thee, and thou art troubled. 6Is not this thy fear, thy confidence, thy hope, and the uprightness of thy ways?

7Remember, I pray thee, who ever perished, being innocent? or where were the righteous cut off? 8Even as I have seen, they that plow iniquity, and sow wickedness, reap the same. 9By the blast of God they perish, and by the breath of his nostrils are they consumed.4.9 by the breath…: that is, by his anger 10The roaring of the lion, and the voice of the fierce lion, and the teeth of the young lions, are broken. 11The old lion perisheth for lack of prey, and the stout lion’s whelps are scattered abroad.

12Now a thing was secretly brought to me, and mine ear received a little thereof.4.12 secretly: Heb. by stealth 13In thoughts from the visions of the night, when deep sleep falleth on men, 14Fear came upon me, and trembling, which made all my bones to shake.4.14 came…: Heb. met4.14 all: Heb. the multitude of 15Then a spirit passed before my face; the hair of my flesh stood up: 16It stood still, but I could not discern the form thereof: an image was before mine eyes, there was silence, and I heard a voice, saying,4.16 there…: or, I heard a still voice 17Shall mortal man be more just than God? shall a man be more pure than his maker? 18Behold, he put no trust in his servants; and his angels he charged with folly:4.18 and his…: or, nor in his angels, in whom he put light 19How much less in them that dwell in houses of clay, whose foundation is in the dust, which are crushed before the moth? 20They are destroyed from morning to evening: they perish for ever without any regarding it.4.20 destroyed: Heb. beaten in pieces 21Doth not their excellency which is in them go away? they die, even without wisdom.