Jobu 36 – YCB & HOF

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 36:1-33

1Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé:

2“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,

nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.

3Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,

èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.

4Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké

nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.

5“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì

gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.

6Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,

ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.

7Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,

ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́;

àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.

8Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a

sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,

9Nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,

wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.

10Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,

ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.

11Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,

wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn,

àti ọdún wọn nínú afẹ́.

12Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,

wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé,

wọ́n á sì kú láìní òye.

13“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;

wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.

14Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,

ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.

15Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,

a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.

16“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,

sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀,

ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.

17Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;

ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.

18Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;

láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.

19Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?

Tàbí ipa agbára rẹ?

20Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké

àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.

21Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú;

Nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.

22“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;

ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?

23Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,

tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?

24Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,

ti ènìyàn ni yín nínú orin.

25Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;

ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè,

26Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,

bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.

27“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,

kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,

28tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,

tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ lórí ènìyàn.

29Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,

tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?

30Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká

ó sì bo ìsàlẹ̀ Òkun mọ́lẹ̀.

31Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;

ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

32Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì

ó sì rán an sí ẹni olódì.

33Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;

ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!

Hoffnung für Alle

Hiob 36:1-33

Wer kann Gott begreifen?

1Weiter sagte Elihu:

2»Hab Geduld mit mir

und hör noch ein wenig zu!

Ich will dir zeigen,

dass man noch viel mehr zu Gottes Verteidigung sagen kann.

3Mein ganzes Wissen will ich aufbieten,

um meinem Schöpfer Recht zu verschaffen.

4Ich sage dir die Wahrheit,

vor dir steht ein Mann, der weiß, wovon er spricht –

darauf kannst du dich verlassen!

5Wie mächtig ist Gott!

Und doch verachtet er keinen.

Ja, mächtig ist er und voll Willenskraft.

6Den Gottlosen lässt er nicht am Leben,

doch dem Unterdrückten verhilft er zum Recht.

7Wer ihm die Treue hält, den vergisst er nicht,

nein, er stellt ihn Königen gleich,

betraut ihn für immer mit einem hohen Amt.

8Und wenn Menschen in Ketten liegen, elend gefangen, mit Stricken gefesselt,

9dann redet er ihnen ins Gewissen,

überführt sie von ihrer Schuld und aller Überheblichkeit.

10Er macht sie bereit, auf seine Zurechtweisung zu hören,

und sagt ihnen, sie sollen vom Unrecht ablassen.

11Wenn sie Gott gehorchen und ihm dienen,

werden sie ihre Lebensjahre glücklich und zufrieden verbringen.

12Hören sie aber nicht auf ihn,

rennen sie in ihr eigenes Verderben;

sie sterben ohne jede Einsicht.

13Wer Gott verworfen hat, der ist bitter gegen ihn;

er fleht nicht einmal dann um Gnade,

wenn Gott die Fesseln enger zieht.

14Und so stirbt er noch in jungen Jahren,

verachtet wie die Männer,

die ihren Körper in den Götzentempeln verkaufen.

15Doch wer sich vor Gott demütigt,

den wird er aus dem Elend retten

und ihn in der Not seine Stimme hören lassen.

16Auch dich reißt Gott aus den Klauen der Angst,

er will dir wieder die Freiheit schenken;

dann füllen die besten Speisen wie früher deinen Tisch.

17Jetzt aber lastet das Urteil auf dir,

das die Gottlosen trifft;

die strafende Gerechtigkeit lässt dich nicht entkommen.

18Pass auf, dass dein Zorn dich nicht zum Spötter macht,

lass dich nicht durch Bestechungsgeld verleiten!

19Kannst du dich etwa selbst aus der Bedrängnis retten?

Niemals! Dazu reicht deine ganze Kraft nicht aus.

20Wünsche dir auch nicht die Nacht herbei,

in der ganze Völker verschwinden!36,20 Die Verse 18‒20 sind nicht sicher zu deuten.

21Sei auf der Hut und wende dich nicht dem Bösen zu!

Denn davor wollte dich Gott durch das Leid ja gerade bewahren.

22Halte dir Gottes große Kraft vor Augen!

Er ist der beste Lehrer, den es gibt!

23Niemand schreibt ihm vor,

was er zu tun hat.

Keiner könnte zu ihm sagen:

›Du hast Unrecht getan!‹

24Schon immer haben die Menschen seine Taten besungen,

nun preise auch du ihn!

25Alle Welt sieht staunend seine Taten,

doch man erblickt sie nur von ferne.

26Wie mächtig ist Gott, wie unbegreiflich!

Wer kann seine Jahre zählen?

27Er lässt die Wassertropfen aufsteigen;

gereinigt gehen sie als Regen in die Flüsse nieder.

28Ja, aus den Wolken strömt der Regen,

auf viele Menschen kommt er herab.

29Wer versteht, wie Gott die Wolken auftürmt

und wie am Himmelszelt der Donner kracht?

30Sieh nur, wie Gott Licht um sich verbreitet,

die Meerestiefen aber verbirgt er.

31Er lässt die Regenwolken kommen,

so richtet er die Völker,

aber zugleich versorgt er sie reichlich mit Nahrung.

32Den Blitzstrahl nimmt er fest in beide Hände

und befiehlt ihm dann, sein Ziel zu treffen.

33Donnergrollen kündigt das Gewitter an,

und selbst das Vieh spürt, dass es kommt.