Jobu 36 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 36:1-33

1Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé:

2“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,

nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.

3Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,

èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.

4Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké

nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.

5“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì

gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.

6Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,

ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.

7Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,

ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́;

àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.

8Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a

sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,

9Nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,

wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.

10Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,

ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.

11Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,

wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn,

àti ọdún wọn nínú afẹ́.

12Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,

wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé,

wọ́n á sì kú láìní òye.

13“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;

wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.

14Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,

ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.

15Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,

a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.

16“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,

sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀,

ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.

17Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;

ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.

18Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;

láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.

19Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?

Tàbí ipa agbára rẹ?

20Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké

àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.

21Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú;

Nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.

22“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;

ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?

23Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,

tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?

24Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,

ti ènìyàn ni yín nínú orin.

25Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;

ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè,

26Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,

bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.

27“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,

kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,

28tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,

tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ lórí ènìyàn.

29Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,

tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?

30Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká

ó sì bo ìsàlẹ̀ Òkun mọ́lẹ̀.

31Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;

ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

32Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì

ó sì rán an sí ẹni olódì.

33Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;

ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!

La Bible du Semeur

Job 36:1-33

Dieu éduque l’homme par la souffrance

1Elihou continua en ces termes :

2Accepte encore un peu ╵que je t’enseigne,

car il y a encore à dire ╵pour la cause de Dieu.

3De loin, je tirerai ma science, ╵oui, de très loin,

et je rendrai justice ╵à celui qui m’a fait.

4Car vraiment, mes discours ╵ne sont pas des mensonges.

Et je m’adresse à toi ╵avec un savoir sûr.

5Bien que puissant, ╵Dieu n’a de dédain pour personne ;

il est puissant, ╵il est aussi déterminé.

6Il ne permettra pas ╵que vive le méchant,

il fait justice aux opprimés,

7il ne détourne pas ╵ses yeux des hommes justes,

mais il les fait asseoir ╵sur un trône à côté des rois.

Il les y établit ╵pour siéger à jamais ; ╵ainsi il les honore.

8S’ils sont liés de chaînes

ou pris dans les liens du malheur,

9c’est qu’il leur dénonce leurs actes,

les fautes que dans leur orgueil ╵ils ont commises.

10Il ouvre leurs oreilles ╵aux avertissements

et il leur dit : ╵« Détournez-vous du mal. »

11S’ils écoutent, et se soumettent,

ils finissent leurs jours ╵dans le bonheur,

et leurs années s’achèvent ╵dans les délices.

12Mais s’ils n’écoutent pas, ╵ils auront à subir ╵les coups du javelot

et ils expireront, ╵faute d’avoir reçu ╵la connaissance.

13Quant à ceux qui rejettent Dieu, ╵ils gardent leur colère36.13 Autre traduction : ils s’exposent à la colère de Dieu.,

ils ne crient pas à l’aide ╵quand il les lie de chaînes.

14Aussi, leur vie s’éteint ╵en pleine fleur de l’âge,

ils la terminent ╵parmi les prostitués sacrés.

15Mais Dieu délivre l’affligé ╵par son affliction même,

et c’est par la souffrance ╵qu’il le dispose à l’écouter.

16Toi aussi, il t’arrachera ╵à la détresse

pour t’établir au large ╵sans rien pour te gêner,

et pour charger ta table ╵d’aliments savoureux.

17Mais maintenant si tu adoptes ╵le jugement des criminels,

la justice et le jugement ╵se saisiront de toi.

18Que la colère ╵ne t’incite donc pas ╵à te moquer de Dieu,

et ne t’égare pas ╵parce que la rançon ╵est bien trop grande36.18 Hébreu obscur. Autre traduction : Prends garde de ne pas te laisser séduire par des largesses, et ne te laisse pas égarer par un pot-de-vin..

19Tes cris suffiraient-ils

ou même tes plus grands efforts, ╵pour te faire échapper ╵à la détresse ?

20Ne soupire donc pas ╵après la nuit

qui balaiera les peuples !

21Fais attention ! ╵Ne te tourne pas vers le mal !

Car la souffrance t’y dispose36.21 Autre traduction : Ne te tourne pas vers le mal que tu préférerais à la souffrance..

22Vois, Dieu est souverain ╵par sa puissance.

Quel maître enseigne comme lui ?

23Qui inspectera sa conduite36.23 Autre traduction : Qui lui dictera sa conduite ? ?

Qui lui a jamais dit : ╵« Ce que tu fais est mal » ?

24Mais souviens-toi plutôt ╵de célébrer son œuvre

que chantent les humains.

25Tout le monde la voit,

tout être humain ╵la regarde de loin.

26Vois combien Dieu est grand : cela dépasse ╵notre compréhension.

Nul ne peut calculer ╵le nombre de ses ans.

27Oui, c’est lui qui attire ╵les gouttelettes d’eau,

il les distille en pluie, ╵il en fait de la brume.

28Les nuées répandent la pluie

et elles la déversent ╵en trombes sur les hommes.

29Qui prétendrait comprendre ╵l’expansion des nuages

et les coups de tonnerre ╵dont retentit sa tente ?

30Vois, tout autour, ╵scintiller ses éclairs ;

c’est lui encore qui recouvre ╵les profondeurs des mers.

31Par tous ces éléments, ╵Dieu régit les nations,

et il pourvoit les hommes ╵de nourriture en abondance.

32Et en ses mains ╵il cache des éclairs

auxquels il assigne une cible.

33Le bruit de son tonnerre ╵annonce sa venue,

et même les troupeaux ╵pressentent son approche.