1Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé:
2“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,
nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
3Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,
èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
4Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké
nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
5“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì
gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
6Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,
ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
7Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,
ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́;
àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
8Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a
sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
9Nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,
wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
10Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,
ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
11Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,
wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn,
àti ọdún wọn nínú afẹ́.
12Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,
wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé,
wọ́n á sì kú láìní òye.
13“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;
wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
14Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,
ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
15Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,
a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
16“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,
sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀,
ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
17Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;
ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
18Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;
láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
19Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?
Tàbí ipa agbára rẹ?
20Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké
àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
21Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú;
Nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
22“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;
ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
23Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,
tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
24Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,
ti ènìyàn ni yín nínú orin.
25Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;
ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè,
26Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,
bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
27“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,
kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
28tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,
tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ lórí ènìyàn.
29Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,
tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
30Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká
ó sì bo ìsàlẹ̀ Òkun mọ́lẹ̀.
31Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;
ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
32Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì
ó sì rán an sí ẹni olódì.
33Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;
ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Dieu éduque l’homme par la souffrance
1Elihou continua en ces termes :
2Accepte encore un peu ╵que je t’enseigne,
car il y a encore à dire ╵pour la cause de Dieu.
3De loin, je tirerai ma science, ╵oui, de très loin,
et je rendrai justice ╵à celui qui m’a fait.
4Car vraiment, mes discours ╵ne sont pas des mensonges.
Et je m’adresse à toi ╵avec un savoir sûr.
5Bien que puissant, ╵Dieu n’a de dédain pour personne ;
il est puissant, ╵il est aussi déterminé.
6Il ne permettra pas ╵que vive le méchant,
il fait justice aux opprimés,
7il ne détourne pas ╵ses yeux des hommes justes,
mais il les fait asseoir ╵sur un trône à côté des rois.
Il les y établit ╵pour siéger à jamais ; ╵ainsi il les honore.
8S’ils sont liés de chaînes
ou pris dans les liens du malheur,
9c’est qu’il leur dénonce leurs actes,
les fautes que dans leur orgueil ╵ils ont commises.
10Il ouvre leurs oreilles ╵aux avertissements
et il leur dit : ╵« Détournez-vous du mal. »
11S’ils écoutent, et se soumettent,
ils finissent leurs jours ╵dans le bonheur,
et leurs années s’achèvent ╵dans les délices.
12Mais s’ils n’écoutent pas, ╵ils auront à subir ╵les coups du javelot
et ils expireront, ╵faute d’avoir reçu ╵la connaissance.
13Quant à ceux qui rejettent Dieu, ╵ils gardent leur colère36.13 Autre traduction : ils s’exposent à la colère de Dieu.,
ils ne crient pas à l’aide ╵quand il les lie de chaînes.
14Aussi, leur vie s’éteint ╵en pleine fleur de l’âge,
ils la terminent ╵parmi les prostitués sacrés.
15Mais Dieu délivre l’affligé ╵par son affliction même,
et c’est par la souffrance ╵qu’il le dispose à l’écouter.
16Toi aussi, il t’arrachera ╵à la détresse
pour t’établir au large ╵sans rien pour te gêner,
et pour charger ta table ╵d’aliments savoureux.
17Mais maintenant si tu adoptes ╵le jugement des criminels,
la justice et le jugement ╵se saisiront de toi.
18Que la colère ╵ne t’incite donc pas ╵à te moquer de Dieu,
et ne t’égare pas ╵parce que la rançon ╵est bien trop grande36.18 Hébreu obscur. Autre traduction : Prends garde de ne pas te laisser séduire par des largesses, et ne te laisse pas égarer par un pot-de-vin..
19Tes cris suffiraient-ils
ou même tes plus grands efforts, ╵pour te faire échapper ╵à la détresse ?
20Ne soupire donc pas ╵après la nuit
qui balaiera les peuples !
21Fais attention ! ╵Ne te tourne pas vers le mal !
Car la souffrance t’y dispose36.21 Autre traduction : Ne te tourne pas vers le mal que tu préférerais à la souffrance..
22Vois, Dieu est souverain ╵par sa puissance.
Quel maître enseigne comme lui ?
23Qui inspectera sa conduite36.23 Autre traduction : Qui lui dictera sa conduite ? ?
Qui lui a jamais dit : ╵« Ce que tu fais est mal » ?
24Mais souviens-toi plutôt ╵de célébrer son œuvre
que chantent les humains.
25Tout le monde la voit,
tout être humain ╵la regarde de loin.
26Vois combien Dieu est grand : cela dépasse ╵notre compréhension.
Nul ne peut calculer ╵le nombre de ses ans.
27Oui, c’est lui qui attire ╵les gouttelettes d’eau,
il les distille en pluie, ╵il en fait de la brume.
28Les nuées répandent la pluie
et elles la déversent ╵en trombes sur les hommes.
29Qui prétendrait comprendre ╵l’expansion des nuages
et les coups de tonnerre ╵dont retentit sa tente ?
30Vois, tout autour, ╵scintiller ses éclairs ;
c’est lui encore qui recouvre ╵les profondeurs des mers.
31Par tous ces éléments, ╵Dieu régit les nations,
et il pourvoit les hommes ╵de nourriture en abondance.
32Et en ses mains ╵il cache des éclairs
auxquels il assigne une cible.
33Le bruit de son tonnerre ╵annonce sa venue,
et même les troupeaux ╵pressentent son approche.