Jobu 34 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 34:1-37

Elihu pe Jobu níjà

1Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,

kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.

3Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò,

bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.

4Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa;

ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.

5“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi;

Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.

6Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,

bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi,

ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’

7Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu,

tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?

8Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó

sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.

9Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,

tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

10“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi,

ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye:

Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú,

àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!

11Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe,

yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.

12Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà;

bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.

13Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́,

tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?

14Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀

tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

15gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,

ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

16“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye,

gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.

17Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí?

Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?

18O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘ènìyàn búburú ní ìwọ,’

tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘ìkà ni ẹ̀yin,’

19Mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé

tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ,

nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?

20Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú,

àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ;

a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

21“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn,

òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú,

níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sápamọ́ sí.

23Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan,

kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí,

a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,

25nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn,

ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.

26Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn

níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,

27nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i,

wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,

28kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀,

òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.

29Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi?

Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i?

Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;

30Kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba

kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.

31“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé,

èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?

32Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi

bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

33Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?

Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́,

ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi.

Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀;

Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!

34“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi,

àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,

35‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀,

ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’

36Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin,

nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú:

37Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀;

ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa,

ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”

Bibelen på hverdagsdansk

Jobs Bog 34:1-37

Elihu påpeger Jobs selvretfærdighed

1Elihu fortsatte:

2„Hør godt efter, I vismænd,

lyt til mig, I som er så kloge.

3Man må vurdere alt, hvad man hører,

ligesom man smager på maden, før man spiser den.

4Lad os derfor i fællesskab finde ud af,

hvad der er sandt og rigtigt.

5Job siger: ‚Jeg er uskyldig,

det er Gud, der gør mig uret.

6Jeg regnes for en løgner, selvom jeg taler sandt,

jeg bliver straffet hårdt, skønt jeg ikke har syndet.’

7Hvor har Job lært at tale sådan?

Det er jo en hån imod Gud.

8Han må have tilbragt sin tid i dårligt selskab

med onde og gudløse mennesker.

9Han påstår jo, at man intet får ud af

at leve retskaffent ind for Gud.

10I vise mænd, vil I ikke give mig ret i,

at det er umuligt for Gud at være ond?

Den Almægtige kan ikke være uretfærdig.

11Nej, vi ved, at han straffer mennesker for, hvad de har gjort.

Han lader dem opleve følgerne af deres synd.

12Gud handler absolut ikke ondt,

den Almægtige er aldrig uretfærdig.

13Han alene har al magt på jorden,

han opretholder og styrer verden.

14Hvis Gud en dag besluttede

at trække sin livsånde til sig igen,

15da ville alt levende uddø,

og menneskene igen blive til støv.

16Tag nu og brug din forstand.

Prøv at forstå, hvad jeg siger.

17Kunne Gud være den almægtige Dommer,

hvis han ikke var uangribelig?

Vil du anklage selve ‚Retfærdigheden’

og påstå, at han kan være uretfærdig?

18Han dømmer konger og regenter

for deres onde og uretfærdige handlinger.

19Han gør ikke forskel på folk,

men behandler rige og fattige ens.

Alle mennesker er jo skabt af Gud,

20og de skal alle sammen dø en gang.

Uden varsel er livet slut,

og ingen kan gøre fra eller til.

21Gud kender alle deres handlinger,

han ser alt, hvad de foretager sig.

22Ingen steder findes så tæt et mørke,

at de onde kan skjule sig for Gud.

23Gud behøver ikke at vente til dommens dag

med at straffe et menneske for dets synder.

24Han afsætter magtfulde ledere uden forhør

og indsætter andre i deres sted,

25for han kender deres onde handlinger

og kan vende deres skæbne på en enkelt nat.

26Han straffer dem for deres ondskab

på en måde, så alle kan se det,

27for de vendte sig bort fra Gud

og var ligeglade med hans vilje.

28Deres magtmisbrug over for de svage

førte til et råb om hjælp, som Gud hørte.

29Selv når Gud er tavs, kan du ikke dømme ham for det.

Hvis han skjuler sig, kan du ikke tvinge ham frem.

Han hersker jo over alt, hvad han har skabt,

30så de gudløse ikke skal have magten

og undertrykke andre mennesker.

31Hvad nu hvis et menneske siger til Gud:

‚Hvis jeg har syndet, vil jeg ikke gøre det mere.

32Sig mig, hvad jeg har gjort forkert.

Hvis jeg har svigtet, lover jeg at forbedre mig.’

33Mon så ikke Gud er nådig,

selv om du benægter, at han er det?

Om du vil bede om nåde, er op til dig.

Sig os, hvad du har i tanke.

34Ethvert forstandigt menneske

vil være enig med mig og sige:

35‚Job taler uden indsigt.

Han ved ikke, hvad han snakker om.’

36Er det mærkeligt, at Job bliver straffet så hårdt?

Han taler jo som de gudløse taler.

37Ud over sin oprindelige synd

gør han nu oprør mod Gud

ved at vise foragt for vores vejledning

og ved stadig at anklage Gud.”