Jobu 33 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 33:1-33

Elihu bá Jobu sọ̀rọ̀

1“Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ,

gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!

2Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi,

ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.

3Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi,

ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.

4Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi,

àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.

5Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,

tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;

6Kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà;

láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.

7Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ;

bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

8“Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi,

èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,

9‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi;

bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.

10Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi;

ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.

11Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà;

o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’

12“Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà!

Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!

13Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé,

òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?

14Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan,

àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.

15Nínú àlá, ní ojúran òru,

nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ,

ní sísùn lórí ibùsùn,

16Nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn,

yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,

17Kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀;

Kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;

18Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú,

àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.

19“A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀;

pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,

20bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ,

ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.

21Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́

egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.

22Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú,

ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.

23Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀,

ẹni tí ń ṣe alágbàwí,

ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,

24Nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé,

gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú;

èmi ti rà á padà.

25Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré,

yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;

26Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀,

o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀,

òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.

27Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé,

‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po,

a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;

28Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò,

ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’

29“Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run

máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,

30Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú,

láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.

31“Jobu, kíyèsi i gidigidi kí o sì fetí sí mi;

pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́

32Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn;

máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.

33Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi;

pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”

Swedish Contemporary Bible

Job 33:1-33

Elihu tillrättavisar Job

1Lyssna nu, Job, till vad jag har att säga,

hör noga på mina ord.

2Nu vill jag öppna min mun,

orden är redan på min tunga.

3Mina ord kommer från ett uppriktigt hjärta,

mina läppar säger ärligt vad jag vet.

4Guds Ande har skapat mig

och den Väldiges ande33:4 Eller livsande, andedräkt. har gett mig liv.

5Svara mig, om du kan,

bemöt mig, var redo!

6Inför Gud är du och jag lika.

Jag är också formad av lera.

7Ingen rädsla för mig ska behöva skrämma dig,

och jag ska inte trycka ner dig.

8Du har sagt så att jag har hört det,

ja, jag har faktiskt fått lyssna till detta:

9”Jag är ren och utan synd,

jag är fläckfri, fri från skuld.

10Ändå granskar han mina fel

och räknar mig som sin fiende.

11Han sätter mina fötter i stocken

och bevakar alla mina vägar.”

12Nu vill jag säga dig:

på denna punkt har du inte rätt!

Gud är större än människor.

13Varför ska du anklaga honom

för att han inte ger dem något svar?

14För Gud talar både på ett sätt och två sätt,

men man märker det inte:

15i en dröm, i en syn om natten,

när människor är i djup sömn,

när de slumrar på sin bädd.

16Han öppnar då människors öron,

han varnar och förskräcker dem

17för att hindra människan från ogärningar,

för att hålla henne borta från högmod.

18Han bevarar henne från graven,

skonar hennes liv för svärdet.

19Människan tuktas av plågor på sin bädd,

av ständig smärta i sin kropp,

20hon tappar matlusten

vill inte ens ha den läckraste mat.

21Hon magrar så att inget finns kvar,

alla dolda ben i kroppen syns nu,

22och hon dras allt närmare graven,

hennes liv allt närmare dödens makter.

23Men om en budbärare kommer från himlen,

en medlare av tusen,

och talar om för henne vad som är rätt,33:23 Grundtextens innebörd är osäker.

24då förbarmar sig Gud över henne och säger:

”Låt henne bli fri.

Låt henne inte gå ner i graven,

för jag har fått lösen för henne.”

25Då förnyas hennes kropp och blir som ett barns,

hon återfår sin ungdomskraft.

26Hon ber till Gud,

och han svarar med välvilja,

låter människan träda fram inför honom

och återställer hennes rättfärdighet.

27Då går människan till andra och säger:

”Jag syndade, jag förvrängde det som var rätt,

men jag fick inte vad jag förtjänade.

28Han lät mig slippa gå ner i graven,

och nu får jag fortsätta att leva i ljuset.”

29Så gör Gud med människan,

både två och tre gånger.

30Han låter henne återvända från graven

och livets ljus lysa över henne.

31Lyssna nu, Job! Hör på mig,

var tyst och låt mig få fortsätta!

32Men om du har något att säga, så gör det nu.

Tala ut, för jag är angelägen om att få ge dig rätt.

33Men om inte, så var tyst och fortsätt att lyssna.

Jag ska lära dig vishet.