Jobu 32 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 32:1-22

Ọ̀rọ̀ Elihu

1Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí dákẹ́ láti dá Jobu lóhùn, nítorí ó ṣe olódodo lójú ara rẹ̀. 2Nígbà náà ni inú bí Elihu ọmọ Barakeli ará Busi, láti ìbátan ìdílé Ramu; ó bínú si Jobu nítorí ti ó dá ara rẹ̀ láre kàkà ki ó dá Ọlọ́run láre. 3Inú sì bí i sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, nítorí tí wọn kò rí ọ̀nà láti dá Jobu lóhùn bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá Jobu lẹ́bi. 4Ǹjẹ́ Elihu ti dúró títí tí Jobu fi sọ̀rọ̀ tán nítorí tí àwọn wọ̀nyí dàgbà ju òun lọ ní ọjọ́ orí. 5Nígbà tí Elihu rí i pé ìdáhùn ọ̀rọ̀ kò sí ní ẹnu àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí nígbà náà ni ó bínú.

6Elihu, ọmọ Barakeli, ará Busi, dáhùn ó sì wí pé:

“Ọmọdé ni èmi,

àgbà sì ní ẹ̀yin;

ǹjẹ́ nítorí náà ní mo dúró,

mo sì ń bẹ̀rù láti fi ìmọ̀ mi hàn yin.

7Èmi wí pé ọjọ́ orí ni ìbá sọ̀rọ̀,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìbá kọ́ ni ní ọgbọ́n.

8Ṣùgbọ́n ẹ̀mí kan ní ó wà nínú ènìyàn

àti ìmísí Olódùmarè ní ì sì máa fún wọn ní òye.

9Ènìyàn ńláńlá kì í ṣe ọlọ́gbọ́n,

Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10“Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé: Ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;

èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.

11Kíyèsi i, èmí ti dúró de ọ̀rọ̀ yín;

Èmi fetísí àròyé yín,

nígbà tí ẹ̀yin ń wá ọ̀rọ̀ ti ẹ̀yin yóò sọ;

12àní, mo fiyèsí yín tinútinú.

Sì kíyèsi i, kò sí ẹnìkan nínú yín tí ó le já Jobu ní irọ́;

tàbí tí ó lè dá a lóhùn àríyànjiyàn rẹ̀!

13Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe wí pé, ‘Àwa wá ọgbọ́n ní àwárí;

Ọlọ́run ni ó lè bì í ṣubú kì í ṣe ènìyàn.’

14Bí òun kò ti sọ̀rọ̀ sí mi,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi ọ̀rọ̀ yín dá a lóhùn.

15“Ẹnu sì yà wọ́n, wọn kò sì dáhùn mọ́,

wọ́n ṣíwọ́ ọ̀rọ̀ í sọ.

16Mo sì retí, nítorí wọn kò sì fọhùn, wọ́n dákẹ́ jẹ́ẹ́;

wọn kò sì dáhùn mọ́.

17Bẹ́ẹ̀ ni èmí ó sì dáhùn nípa ti èmi,

èmí pẹ̀lú yóò sì fi ìmọ̀ mi hàn.

18Nítorí pé èmi kún fún ọ̀rọ̀ sísọ,

ẹ̀mí ń rọ̀ mi ni inú mi.

19Kíyèsi i, ikùn mi dàbí ọtí wáìnì, tí kò ní ojú-ìhò;

ó múra tán láti bẹ́ bí ìgò-awọ tuntun.

20Èmí ó sọ, kí ara kí ó le rọ̀ mí,

èmí ó sí ètè mi, èmí ó sì dáhùn.

21Lóòtítọ́ èmi kì yóò ṣe ojúsàájú sí ẹnìkankan,

bẹ́ẹ̀ ni èmí kì yóò sì ṣe ìpọ́nni fún ẹnìkan.

22Nítorí pé èmí kò mọ̀ ọ̀rọ̀ ìpọ́nni í sọ ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀,

Ẹlẹ́dàá mi yóò mú mi kúrò lọ́gán.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Job 32:1-22

Intervención de Eliú

1Al ver los tres amigos de Job que este se consideraba un hombre recto, dejaron de responderle. 2Pero Eliú hijo de Baraquel de Buz, de la familia de Ram, se enojó mucho con Job porque, en vez de justificar a Dios, se había justificado a sí mismo. 3También se enojó con los tres amigos porque no habían logrado refutar a Job, y sin embargo lo habían condenado. 4Ahora bien, Eliú había estado esperando antes de dirigirse a Job, porque ellos eran mayores; 5pero, al ver que los tres amigos no tenían ya nada que decir, se encendió su enojo. 6Y habló Eliú hijo de Baraquel de Buz:

Primer discurso de Eliú

«Yo soy muy joven, y vosotros, ancianos;

por eso me sentía muy temeroso

de expresaros mi opinión.

7Y me dije: “Que hable la voz de la experiencia;

que demuestren los ancianos su sabiduría”.

8Pero lo que da entendimiento al hombre

es el espíritu32:8 espíritu. Alt. Espíritu; también en v. 18. que en él habita;

¡es el hálito del Todopoderoso!

9No son los ancianos32:9 ancianos. Alt. muchos, o grandes. los únicos sabios,

ni es la edad la que hace entender lo que es justo.

10»Os ruego, por tanto, que me escuchéis;

yo también tengo algo que deciros.

11Mientras habláis, me propuse esperar

y escuchar vuestros razonamientos;

mientras buscabais las palabras,

12os presté toda mi atención.

Pero no habéis podido probar que Job esté equivocado;

ninguno ha respondido a sus argumentos.

13No vayáis a decirme: “Hemos hallado la sabiduría;

que lo refute Dios, y no los hombres”.

14Ni Job se ha dirigido a mí,

ni yo he de responderle como vosotros.

15»Job, tus amigos están desconcertados;

no pueden responder, les faltan las palabras.

16¿Y voy a quedarme callado ante su silencio,

ante su falta de respuesta?

17Yo también tengo algo que decir,

y voy a demostrar mis conocimientos.

18Palabras no me faltan;

el espíritu que hay en mí me obliga a hablar.

19Estoy como vino embotellado

en odre nuevo a punto de estallar.

20Tengo que hablar y desahogarme;

tengo que abrir la boca y dar respuesta.

21No favoreceré a nadie

ni halagaré a ninguno;

22Yo no sé adular a nadie;

si lo hiciera,32:22 si lo hiciera. Lit. en poco tiempo. mi creador me castigaría.