Jobu 28 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 28:1-28

Ọ̀rọ̀ ọgbọ́n àti òye Jobu

1Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ,

àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.

2Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,

bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.

3Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn,

ó sì ṣe àwárí ìṣúra

láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.

4Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè,

àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀,

wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.

5Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,

àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná

6Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Safire,

o sì ní erùpẹ̀ wúrà.

7Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀,

àti ojú gúnnugún kò rí i rí;

8Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí,

bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.

9Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta,

ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.

10Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta,

ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.

11Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya,

ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.

12Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí,

níbo sì ni òye ń gbe?

13Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.

14Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”;

omi Òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”

15A kò le è fi wúrà rà á,

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òṣùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.

16A kò le è fi wúrà ofiri,

tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta Safire díye lé e.

17Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.

18A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi;

iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.

19Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀;

bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.

20Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?

Tàbí níbo ni òye ń gbé?

21A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo,

ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.

22Ibi ìparun àti ikú wí pé,

àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.

23Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀,

òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.

24Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé,

ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,

25Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́,

ó sì fi òṣùwọ̀n wọ́n omi.

26Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò,

tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,

27Nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde;

ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.

28Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,

“Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n,

àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”

New Russian Translation

Иов 28:1-28

Поэма о мудрости

1– Есть рудник для серебра

и для золота есть горн плавильный.

2Из земли добывают железо,

и плавят медь из руды.

3Тьме рудокоп полагает предел.

Ищет он в отдаленных пределах

руду в непроглядной мгле.

4Далеко от жилья он роет колодец,

в местах, что забыла стопа человека;

висит он и зыблется вдали от людей.

5Земля, на которой вырастает пища,

изнутри изрыта, будто огнем.

6Сапфиров28:6 Или: «лазурита»; также в ст. 16. россыпь в ее камнях,

и в ней – золотой песок.

7Пути к ним не знает хищная птица,

соколиный глаз их не видел.

8Гордые звери их не топтали,

и лев по ним не ходил.

9Человек на гранит простирает руку

и с корнем вырывает горы.

10Он прорубает проходы в скалах,

и глаза его видят все их сокровища.

11Он останавливает28:11 Или: «ищет». истоки рек,

и сокровенное выносит на свет.

12Но где можно найти мудрость?

Где обитает разум?

13Не знает смертный ее дома28:13 Или: «ей цены».;

на земле живых ее не найти.

14Пучина скажет: «Во мне ее нет»;

и молвит море: «Не у меня она».

Мудрость ценнее драгоценных камней

15Ее не купить за червонное золото,

не отвесить цену ее серебром.

16Не купить ее ни за золото Офира,

ни за драгоценный оникс и сапфир.

17Не сравнить ее с золотом и кристаллом28:17 Букв.: «стеклом». В древнем мире стекло считалось редким и ценным материалом.,

на утварь из чистого золота не обменять.

18Что говорить о кораллах и яшме;

превыше рубинов стоимость мудрости.

19Не сравнить с ней топазы из Куша28:19 Или: «Нубии»; или: «Ефиопии».;

не купить ее за отменное золото.

20Откуда приходит мудрость?

Где обитает разум?

21Скрыта она от глаз всех живущих

и от птиц небесных утаена.

22Погибель и Смерть говорят:

«Мы слышали только слух о ней».

Только Бог знает пути мудрости

23Только Богу ведом к ней путь,

Он знает ее жилище,

24ведь Он озирает края земли

и видит все, что под небесами.

25Когда Он давал ветру силу

и водам ставил пределы,

26когда Он дождю предписал устав

и путь проложил для молний,

27Он увидел мудрость и восхвалил ее,

утвердил ее, испытал

28и сказал человеку так:

«Воистину, страх перед Владыкой – вот мудрость,

сторониться зла – это разум».