Jobu 20 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 20:1-29

Ìdáhùn Sofari

1Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé:

2“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn,

àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.

3Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye

mi sì dá mi lóhùn.

4“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,

5pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni,

àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?

6Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run,

ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;

7Ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀;

àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’

8Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,

àní a ó lé e lọ bi ìran òru.

9Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,

bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.

10Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà,

ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.

11Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀,

tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.

12“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀,

bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,

13bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,

tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,

14Ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà,

ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;

15Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde;

Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.

16Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú;

ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.

17Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì,

ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.

18Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì;

gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.

19Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti kẹ́hìndà wọ́n;

Nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.

20“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀,

kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.

21Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;

Nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.

22Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;

àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.

23Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun,

Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,

yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.

24Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn;

ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.

25O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára;

idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá.

Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;

26òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀.

Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run

yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.

27Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn,

ayé yóò sì dìde dúró sí i.

28Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun

ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.

29Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,

àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

Nueva Versión Internacional

Job 20:1-29

Segundo discurso de Zofar

1A esto respondió Zofar de Namat:

2«Mis turbados pensamientos me hacen replicar,

pues me hallo muy desconcertado.

3He escuchado una reprensión que me deshonra

y mi inteligencia me obliga a responder.

4»Bien sabes tú que desde antaño,

desde que Dios puso al ser humano20:4 al ser humano. Alt. a Adán. en la tierra,

5muy breve ha sido la algarabía del malvado

y la alegría del impío ha sido pasajera.

6Aunque su orgullo llegue hasta los cielos

y alcance a tocar con la cabeza las nubes,

7él perecerá para siempre, como su excremento,

y sus allegados dirán: “¿Qué se hizo?”.

8Como un sueño, como una visión nocturna,

se desvanecerá y no volverá a ser hallado.

9Los ojos que lo vieron no volverán a verlo;

su lugar no volverá a contemplarlo.

10Sus hijos tendrán que indemnizar a los pobres;

ellos mismos restituirán las riquezas de su padre.

11El vigor juvenil que hoy sostiene sus huesos

un día reposará en el polvo con él.

12»Aunque en su boca el mal sabe dulce

y lo disimula bajo la lengua,

13y aunque no lo suelta para nada,

sino que tenazmente lo retiene,

14ese pan se le agriará en el estómago;

dentro de él se volverá veneno de áspid.

15Vomitará las riquezas que se engulló;

Dios hará que las arroje de su vientre.

16Chupará veneno de serpientes;

la lengua de un áspid lo matará.

17No disfrutará de los arroyos,

de los ríos de crema y miel;

18no se engullirá las ganancias de sus negocios;

no disfrutará de sus riquezas,

19porque oprimió al pobre y lo dejó sin nada,

y se adueñó de casas que nunca construyó.

20»Su ambición nunca quedó satisfecha;

no se salvará con su tesoro.

21Nada se libró de su voracidad;

por eso no perdurará su bienestar.

22En medio de la abundancia, lo abrumará la angustia;

le sobrevendrá toda la fuerza de la desgracia.

23Cuando el malvado se haya llenado el vientre,

Dios dará rienda suelta a su enojo contra él

y descargará sobre él sus golpes.

24Aunque huya de las armas de hierro,

una flecha de bronce lo atravesará.

25Cuando del hígado y de la espalda

intente sacarse la punta de la flecha,

se verá sobrecogido de espanto,

26y la oscuridad total acechará sus tesoros.

Un fuego no atizado acabará con él

y con todo lo que haya quedado de su casa.

27Los cielos harán pública su culpa;

la tierra se levantará a denunciarlo.

28En el día de la ira de Dios,

un aluvión arrasará con su casa.

29Tal es el fin que Dios reserva al malvado;

tal es la herencia que le asignó».