Jobu 20 – YCB & NASV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 20:1-29

Ìdáhùn Sofari

1Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé:

2“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn,

àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.

3Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye

mi sì dá mi lóhùn.

4“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,

láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,

5pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni,

àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?

6Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run,

ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;

7Ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀;

àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’

8Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,

àní a ó lé e lọ bi ìran òru.

9Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,

bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.

10Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà,

ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.

11Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀,

tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.

12“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀,

bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,

13bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,

tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,

14Ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà,

ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;

15Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde;

Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.

16Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú;

ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.

17Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì,

ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.

18Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì;

gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.

19Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti kẹ́hìndà wọ́n;

Nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.

20“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀,

kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.

21Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;

Nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.

22Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;

àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.

23Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun,

Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,

yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.

24Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn;

ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.

25O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára;

idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá.

Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;

26òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀.

Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run

yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.

27Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn,

ayé yóò sì dìde dúró sí i.

28Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun

ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.

29Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,

àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 20:1-29

ሶፋር

1ናዕማታዊውም ሶፋር እንዲህ ሲል መለሰ፤

2“እጅግ ታውኬአለሁና፣

ሐሳቤ መልስ እንድሰጥ ይጐተጕተኛል።

3የሚያቃልለኝን ንግግር ሰምቼአለሁ፤

መልስም እሰጥ ዘንድ መንፈሴ ገፋፋኝ።

4“ሰው20፥4 ወይም አዳም ማለት ነው። በምድር ላይ ከተቀመጠ ጊዜ ጀምሮ፣

ከጥንቱ እንዴት እንደ ነበረ ታውቃለህን?

5የኀጢአተኞች መፈንጨት ለዐጭር ጊዜ፣

የክፉዎችም ደስታ ለቅጽበት መሆኑን አታውቅምን?

6እስከ ሰማይ ከፍ ከፍ ቢልም፣

ዐናቱም ደመናትን ቢነካ፣

7እንደ ኵበት ለዘላለም ይጠፋል፤

ቀድሞ ያዩትም፣ ‘የት ገባ?’ ይላሉ።

8እንደ ሕልም በርሮ ይጠፋል፤ አይገኝምም፤

እንደ ሌሊትም ራእይ በቅጽበት ያልፋል።

9ቀድሞ ያየው ዐይን ዳግመኛ አያየውም፤

የነበረበትም ቦታ ከእንግዲህ አይመለከተውም።

10ልጆቹ ለድኾች ካሳ መክፈል አለባቸው፤

እጆቹም ሀብቱን መልሰው መስጠት ይገባቸዋል።

11ዐጥንቱን የሞላው የወጣትነት ብርታት፣

ከእርሱ ጋር በዐፈር ውስጥ ይተኛል።

12“ክፋት በአፉ ውስጥ ቢጣፍጥ፣

ከምላሱም በታች ቢደብቀው፣

13አውጥቶ ለመጣል እየሳሳ፣

በአፉ ውስጥ ቢያቈየው፣

14ምግቡ በሆዱ ውስጥ ይመርራል፤

በውስጡም እንደ እባብ መርዝ ይሆናል።

15የዋጠውን ሀብት ይተፋል፤

እግዚአብሔርም መልሶ ከሆዱ ያወጣዋል።

16የእባብ መርዝ ይጠባል፤

የእፉኝትም ምላስ ይገድለዋል።

17ማርና ቅቤ በሚያፈስሱ ጅረቶች፣

በወንዞችም አይደሰትም።

18የለፋበትን ሳይበላው ይመልሳል፤

ከንግዱም ባገኘው ትርፍ አይደሰትም፤

19ድኾችን በመጨቈን ባዶ

አስቀርቷቸዋልና፣ ያልሠራውንም ቤት ነጥቋል።

20“ክፉ ምኞቱ ዕረፍት አይሰጠውም

ሀብቱም ሊያድነው አይችልም።

21ያለውን አሟጥጦ ስለሚበላ፣

ዘላቂ ብልጽግና አይኖረውም።

22በተድላ መካከል እያለ ጕስቍልና ይመጣበታል፤

በከባድ መከራም ይዋጣል።

23ሆዱን በሞላ ጊዜ፣

እግዚአብሔር የሚነድድ ቍጣውን ይሰድበታል፤

መዓቱንም ያወርድበታል።

24ከብረት መሣሪያ ቢሸሽም፣

የናስ ቀስት ይወጋዋል።

25ቀስቱን ከጀርባው፣

የሚያብለጨልጨውንም ጫፍ ከጕበቱ ይመዝዛል፤

ፍርሀትም ይይዘዋል፤

26ሀብቱ ለድቅድቅ ጨለማ ተዳርጓል፤

ሰው ባላራገበው እሳት ይበላል፤

በድንኳኑም ውስጥ የተረፈውን ይልሳል።

27ሰማያት ኀጢአቱን ይገልጡበታል፤

ምድርም ትነሣበታለች፤

28በእግዚአብሔር የቍጣ ቀን ቤቱን ጐርፍ፣

መኖሪያውንም ወራጅ ውሃ20፥28 ወይም በቤቱ ውስጥ ያለውን ንብረት ወራጅ ውሃ ይወስድበታል ማለት ነው። ይወስድበታል።

29እግዚአብሔር ለኀጢአተኞች የወሰነው ዕድል ፈንታ፣

ከአምላክም ዘንድ የተመደበላቸው ቋሚ ቅርስ ይህ ነው።”