Jobu 19 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 19:1-29

Ìdáhùn Jobu fún Bilidadi

1Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí,

tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?

3Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí;

ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.

4Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́,

ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.

5Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́,

tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,

6Kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú,

ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.

7“Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi;

mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.

8Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá,

Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.

9Ó ti bọ́ ògo mi,

ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.

10Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo,

ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.

11Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi,

ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.

12Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi,

wọ́n sì mọ odi yí mi ká,

wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.

13“Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré,

àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.

14Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn,

àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.

15Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì;

èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.

16Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn;

mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.

17Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi

ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.

18Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín:

Mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.

19Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi,

àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.

20Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi,

mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.

21“Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi,

ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.

22Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí

Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?

23“Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi

nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!

24Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ

wọ́n sínú àpáta fún láéláé.

25Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè

àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;

26Àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara

mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,

27Ẹni tí èmi ó rí fún ara mi,

tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn;

ọkàn mi sì dákú ní inú mi.

28“Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘àwa ó ti lépa rẹ̀ tó!

Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’

29Kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù;

nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà,

Kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”

Nouă Traducere În Limba Română

Iov 19:1-29

Răspunsul lui Iov

1Iov a răspuns și a zis:

2„Până când îmi veți chinui sufletul

și mă veți zdrobi cu vorbe?

3De zece ori3 Sau: de multe ori. m‑ați batjocorit.

Nu v‑a fost rușine să mă insultați.

4Dacă într-adevăr am greșit,

greșeala mea rămâne cu mine peste noapte.

5Dacă într-adevăr vă înălțați împotriva mea

și folosiți rușinea mea drept dovadă împotriva mea,

6să știți atunci că Dumnezeu a greșit față de mine

și m‑a înconjurat cu lațul Lui.

7Iată, strig: «Violență!», dar nu mi se răspunde;

strig după ajutor, dar nu este dreptate.

8El mi‑a tăiat calea și nu mai pot trece,

El mi‑a învăluit cărările în întuneric.

9M‑a dezbrăcat de gloria mea

și mi‑a smuls coroana de pe cap.

10Mă dărâmă de jur împrejur și sunt dus;

îmi smulge speranța ca pe un copac.

11Mânia Lui s‑a aprins împotriva mea;

mă consideră unul dintre vrăjmașii Săi.

12Oștile Lui pornesc în forță,

au ridicat o rampă de asalt în drumul lor către mine,

și‑au așezat tabăra în jurul cortului meu.

13Mi‑a îndepărtat frații de mine,

cunoscuții mei s‑au înstrăinat de mine.

14Rudele mele m‑au părăsit,

și prietenii m‑au uitat.

15Sunt un străin pentru oaspeții și roabele15 Vezi 31:13. mele;

în ochii lor sunt un necunoscut.

16Îmi chem slujitorul, dar el nu‑mi răspunde,

deși caut bunăvoința lui cu gura mea.

17Suflarea mea stârnește repulsie soției mele,

și sunt dezgustător pentru fiii mamei mele.17 Lit.: fiii pântecului meu.

18Chiar și copiii mă resping;

când mă ridic, ei vorbesc împotriva mea.

19Toți prietenii mei apropiați mă disprețuiesc;

cei pe care‑i iubesc s‑au întors împotriva mea.

20Mi se lipesc oasele de carne;

n‑am rămas decât cu pielea dinților mei.

21Arătați bunăvoință față de mine, prietenii mei, arătați bunăvoință față de mine,

pentru că m‑a lovit mâna lui Dumnezeu!

22De ce mă urmăriți ca Dumnezeu

și nu vă mulțumiți cu carnea mea?

23O, aș vrea să‑mi fie scrise cuvintele,

să fie scrise pe un sul,

24să fie săpate în stâncă pentru totdeauna,

cu o daltă de fier și cu plumb!

25Dar eu știu că Răscumpărătorul25 Sau: Apărătorul. meu este viu

și că, la urmă, va sta pe țărână.

26Chiar după ce pielea mi‑a fost nimicită,

în trup fiind26 Sau: despărțit de trupul meu., Îl voi vedea pe Dumnezeu.

27Îl voi vedea de partea mea,

Îl voi vedea cu ochii mei, și nu‑mi va mai fi un străin27 Sau: Îl voi vedea eu însumi, / ochii mei Îl vor vedea, și nu ai altuia.!

Mi se mistuie rărunchii înăuntrul meu.25-27 Sau: pe pământ, 26chiar dacă pielea îmi va fi nimicită. / Să‑L văd pe Dumnezeu, în trup fiind, / să‑L văd de partea mea, 27 să‑l văd cu ochii mei, să nu‑mi mai fie un străin. De dorul acesta mă mistui înăuntrul meu.

28Veți spune atunci: «De ce îl urmăream?»

Și astfel rădăcina adevărului va fi găsită în mine.

29Temeți‑vă de sabie,

căci mânia aduce pedeapsa sabiei,

ca să știți că există o judecată.“