Jobu 19 – YCB & JCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 19:1-29

Ìdáhùn Jobu fún Bilidadi

1Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí,

tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?

3Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí;

ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.

4Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́,

ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.

5Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́,

tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,

6Kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú,

ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.

7“Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi;

mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.

8Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá,

Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.

9Ó ti bọ́ ògo mi,

ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.

10Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo,

ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.

11Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi,

ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.

12Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi,

wọ́n sì mọ odi yí mi ká,

wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.

13“Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré,

àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.

14Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn,

àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.

15Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì;

èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.

16Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn;

mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.

17Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi

ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.

18Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín:

Mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.

19Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi,

àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.

20Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi,

mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.

21“Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi,

ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.

22Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí

Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?

23“Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi

nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!

24Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ

wọ́n sínú àpáta fún láéláé.

25Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè

àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;

26Àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara

mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,

27Ẹni tí èmi ó rí fún ara mi,

tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn;

ọkàn mi sì dákú ní inú mi.

28“Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘àwa ó ti lépa rẹ̀ tó!

Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’

29Kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù;

nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà,

Kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”

Japanese Contemporary Bible

ヨブ 記 19:1-29

19

ヨブのことば

1ヨブの返答。

2「いつまで、あなたたちは私を悩ませ、

いい加減な論法で言いくるめようとするのか。

3もう十回も、私が罪人だと決めつけた。

そんなにひどく私を責め立てて、

恥ずかしいと思わないのか。

4私が悪いとしても、

あなたがたはまだ、その事実を証明していない。

5何もかもお見通しだと思っているようだが、

それなら、私の落度を証明してみるがよい。

6いま言えることは、神が私を押し倒し、

網で生け捕りにしたということだ。

7必死に助けを求めても、だれも相手にしてくれない。

声を限りに叫んでも、人間扱いさえしてもらえない。

8神は私の道を遮断し、光を闇に変えた。

9私の栄光をはぎ取り、冠を取り上げた。

10私はとことんまで打ちのめされ、虫の息となった。

もうおしまいだ。

11神は私を敵視し、私に向かって怒りを燃やす。

12神の送った軍勢は、

私の回りを二重三重に取り囲む。

13神は兄弟や友人たちまで遠ざけた。

14親族は私を裏切り、友人も私を見捨てた。

15家の者は、召使でさえ、私を赤の他人のように扱う。

私は神を知らない外国人と同じ扱いを受けている。

16召使は呼んでも来ない。

こちらが手をついてお願いするしまつだ。

17妻や兄弟からも、嫌われてしまった。

18年端もゆかぬ子どもまでがさげすむ。

起き上がって話しかけようとすると、あざけり笑う。

19親友は私を毛虫のように嫌い、

手塩にかけてきた者たちも背いた。

20私は骨と皮ばかりになり、かろうじて助かったのだ。

21友よ、お願いだ。

神の怒りの手で打たれた、私の身にもなってくれ。

22神といっしょになって、私をいじめないでくれ。

これだけ私の悩みを見れば満足だろう。

23-24ああ、この訴えを鉄のペンで岩に書きつけ、

いつまでも残せたらよいのに。

25だが、私は知っている。

私を救うお方は生きておられ、

ついには地上に降り立つのだ。

26この肉体が朽ち果てたのち、

私は新しい肉体で神を見る。

27そのとき、

神は私の味方になってくださるはずだ!

そうだ、その時私の目に映る神は、

見も知らぬお方ではなく、

親しい友人であるはずだ!

ああ、何とすばらしい希望だろう。

28なのにあなたたちは、私の刑が確定したかのように、

臆面もなく私を責め立てている。

29警告しておこう。

そんな態度をとっていれば、

あなたたちも罰せられることを忘れてはならない。」