Jobu 17 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 17:1-16

Ìdáhùn Jobu

1“Ẹ̀mí mi bàjẹ́,

ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú,

isà òkú dúró dè mí.

2Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi,

ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.

3“Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́;

ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?

4Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye;

nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.

5Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè,

òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.

6“Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn;

níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.

7Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́,

gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.

8Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí,

ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.

9Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú,

àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.

10“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín,

ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí;

èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.

11Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá,

àní ìrò ọkàn mi.

12Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán;

wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.

13Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi;

mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn.

14Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi,

àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,

15ìrètí mi ha dà nísinsin yìí?

Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?

16Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú,

nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?”

Nouă Traducere În Limba Română

Iov 17:1-16

1Duhul meu este zdrobit,

zilele mele se sting,

mormintele mă așteaptă.

2Nu sunt batjocurile lângă mine?

Ochii mei înnoptează alături de răzvrătirea lor.

3Te rog, pune‑Te chezaș pentru mine!

Cine altcineva ar putea garanta pentru mine?

4Pentru că le‑ai ascuns inima în fața chibzuinței,

de aceea nu‑i vei lăsa să triumfe.

5Cel ce‑și trădează prietenii pentru câștig,

copiilor aceluia li se vor închide ochii.

6El m‑a făcut de pomină printre oameni

și am devenit unul în fața căruia se scuipă.

7Ochii mi se‑ntunecă de durere

și toate mădularele mele sunt ca o umbră.

8Cei drepți sunt înmărmuriți când văd aceasta;

cel nevinovat se ridică împotriva celui lipsit de evlavie.

9Totuși, cel drept se ține de calea lui

și cel cu mâinile curate va fi și mai tare.

10Cât despre voi toți, întoarceți‑vă, veniți acum!

Nu voi găsi însă niciun înțelept între voi.

11Zilele mi‑au trecut, planurile mi s‑au risipit

și chiar și dorințele inimii mele.

12Oamenii aceștia fac din noapte zi

și în prezența întunericului zic: «Lumina este aproape!»

13Dacă aștept ca Locuința Morților să fie casa mea,

dacă îmi întind culcușul în întuneric,

14dacă strig gropii: «Ești tatăl meu!»

și viermelui: «Mama mea!» sau «Sora mea!»,

15unde mai este atunci speranța mea?

Cine va vedea speranța mea?

16Se va coborî ea la porțile Locuinței Morților?

Vom coborî împreună în țărână?“