Jobu 15 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 15:1-35

Elifasi tako ọrọ̀ Jobu

1Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé:

2“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán, kí

ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?

3Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní

èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?

4Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì,

ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.

5Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀

rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.

6Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;

àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.

7“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí?

Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?

8Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí, tàbí

ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?

9Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀?

Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?

10Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa,

tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.

11Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?

Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?

12Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri,

kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.

13Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run,

tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?

14“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́,

àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?

15Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,

àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,

16mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí,

tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.

17“Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi;

Èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,

18ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti

ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,

19Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,

ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.

20Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá,

pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo,

àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.

21Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;

nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.

22Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn;

a sì ṣà á sápá kan fún idà.

23Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà?

Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.

24Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un

bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.

25Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì

sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,

26Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga,

àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.

27“Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀

lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.

28Òun sì gbé inú ahoro ìlú,

àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé

mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.

29Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò

lè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

30Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn;

ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀,

àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.

31Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ.

Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.

32A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀,

ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.

33Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù,

yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.

34Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè

yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

35Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀,

ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”

Nueva Versión Internacional

Job 15:1-35

Segundo discurso de Elifaz

1Replicó entonces Elifaz de Temán:

2«El sabio no responde con vana sabiduría

ni da respuestas en el aire.15:2 ni da respuestas en el aire. Lit. llena su vientre con el viento del este.

3Tampoco discute con argumentos vanos

ni con palabras huecas.

4Tú, en cambio, restas valor al temor a Dios

y tomas a la ligera la devoción que él merece.

5Tu maldad pone en acción tu boca;

hablas igual que la gente astuta.

6Tu propia boca te condena, no la mía;

tus propios labios atestiguan contra ti.

7»¿Eres acaso el primer hombre que ha nacido?

¿Naciste acaso antes que los montes?

8¿Tienes parte en el consejo de Dios?

¿Acaso eres tú el único sabio?

9¿Qué sabes tú que nosotros no sepamos?

¿Qué has percibido que nosotros ignoremos?

10Las canas y la edad están de nuestra parte;

tenemos más experiencia que tu padre.

11¿No te basta que Dios mismo te consuele

y que se te hable con cariño?

12¿Por qué te dejas llevar por el enojo?

¿Por qué te relampaguean los ojos?

13¿Por qué desatas tu enojo contra Dios

y das rienda suelta a tu lengua?

14»¿Qué es el hombre para creerse puro

y el nacido de mujer para alegar inocencia?

15Si Dios no confía ni en sus santos

y ni siquiera considera puros a los cielos,

16¡cuánto menos confiará en el hombre,

que es vil y corrupto y tiene sed del mal!15:16 tiene sed del mal. Lit. bebe como agua el mal.

17»Escúchame y te lo explicaré;

déjame decirte lo que he visto.

18Es lo que han declarado los sabios

sin ocultar nada de lo aprendido de sus antepasados.

19Solo a ellos se les dio la tierra

y ningún extraño pasó entre ellos.

20El impío se ve atormentado toda la vida;

el violento tiene sus años contados.

21Sus oídos perciben sonidos espantosos;

cuando está en paz, los salteadores lo atacan.

22No espera escapar de las tinieblas;

condenado está a morir a filo de espada.

23Vaga sin rumbo; es comida de los buitres;15:23 rumbo … buitres. Alt. rumbo, en busca de alimento.

sabe que el día de las tinieblas le ha llegado.

24La desgracia y la angustia lo llenan de terror;

lo abruman como si un rey fuera a atacarlo

25y todo por levantar el puño contra Dios

y atreverse a desafiar al Todopoderoso.

26Contra Dios se lanzó desafiante,

blandiendo grueso y resistente escudo.

27»Aunque su rostro esté hinchado de grasa

y le sobre carne en la cintura,

28habitará en lugares desolados,

en casas deshabitadas,

en casas a punto de derrumbarse.

29Dejará de ser rico; no durarán sus riquezas

ni se extenderán sus posesiones en la tierra.

30No podrá escapar de las tinieblas;

una llama de fuego marchitará sus renuevos

y el aliento de Dios lo arrebatará.

31Que no se engañe ni confíe en cosas vanas,

porque nada obtendrá a cambio de ellas.

32Antes de que muera recibirá su merecido

y sus ramas no reverdecerán.

33Quedará como vid que pierde sus uvas agrias,

como olivo que no llega a florecer.

34La compañía de los impíos no es de provecho;

¡las moradas de los que aman el soborno serán consumidas por el fuego!

35Conciben iniquidad y dan a luz maldad;

en su vientre se genera el engaño».