Jobu 14 – YCB & NASV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 14:1-22

Jobu tẹ̀síwájú nínú àròyé rẹ̀

1“Ènìyàn tí a bí nínú obìnrin,

ọlọ́jọ́ díẹ̀ ni, ó sì kún fún ìpọ́njú.

2Ó jáde wá bí ìtànná ewéko, a sì ké e lulẹ̀;

ó sì ń fò lọ bí òjìji, kò sì dúró pẹ́.

3Ìwọ sì ń ṣíjú rẹ wò irú èyí ni?

Ìwọ sì mú mi wá sínú ìdájọ́ pẹ̀lú rẹ?

4Ta ni ó lè mú ohun mímọ́ láti inú àìmọ́ jáde wá?

Kò sí ẹnìkan!

5Ǹjẹ́ a ti pinnu ọjọ́ rẹ̀,

iye oṣù rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;

Ìwọ ti pààlà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní òun kò le kọjá rẹ̀.

6Yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kí ó lè

sinmi, títí yóò fi pé ọjọ́ rẹ̀ bí alágbàṣe.

7“Nítorí pé ìrètí wà fún igi, bí a bá

ké e lulẹ̀, pé yóò sì tún sọ,

àti pé ẹ̀ka rẹ̀ tuntun kì yóò gbẹ.

8Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ogbó nínú ilẹ̀,

tí kùkùté rẹ̀ si kú ni ilẹ̀;

9Síbẹ̀ nígbà tí ó bá gbóòórùn omi,

yóò sọ, yóò sì yọ ẹ̀ka jáde bí irúgbìn.

10Ṣùgbọ́n ènìyàn kú, a sì dàánù;

Àní ènìyàn jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́: Òun kò sì sí mọ́.

Àgékúrú ọjọ́ ọmọ ènìyàn

11“Bí omi ti í tán nínú ipa odò,

àti bí odò ṣì tí í fà tí sì gbẹ,

12bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn dùbúlẹ̀ tí kò sì dìde mọ́;

títí ọ̀run kì yóò fi sí mọ́,

wọ́n kì yóò jí, a kì yóò jí wọn kúrò lójú oorun wọn.

13“Háà! ìwọ ìbá fi mí pamọ́ ní ipò òkú,

kí ìwọ kí ó fi mí pamọ́ ní ìkọ̀kọ̀,

títí ìbínú rẹ yóò fi rékọjá,

ìwọ ìbá lànà ìgbà kan sílẹ̀ fún mi, kí ó si rántí mi!

14Bí ènìyàn bá kú yóò sì tún yè bí?

Gbogbo ọjọ́ ìgbà tí a là sílẹ̀

fún mi ni èmi dúró dè, títí àmúdọ̀tún mi yóò fi dé.

15Ìwọ ìbá pè, èmi ìbá sì dá ọ lóhùn;

ìwọ ó sì ní ìfẹ́ sì iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

16Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ń kaye ìṣísẹ̀ mi;

ìwọ kò fa ọwọ́ rẹ kúrò nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi?

17A fi èdìdì di ìrékọjá mi sínú àpò,

ìwọ sì rán àìṣedéédéé mi pọ̀.

18“Àti nítòótọ́ òkè ńlá tí ó ṣubú, ó dasán,

a sì ṣí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀.

19Omi a máa yinrin òkúta, ìwọ a sì

mú omi sàn bo ohun tí ó hù jáde lórí ilẹ̀,

ìwọ sì sọ ìrètí ènìyàn dí òfo.

20Ìwọ ṣẹ́gun rẹ̀ láéláé, òun sì kọjá lọ!

Ìwọ pa awọ ojú rẹ̀ dà, o sì rán an lọ kúrò.

21Àwọn ọmọ rẹ̀ bọ́ sí ipò ọlá, òun kò sì mọ̀;

wọ́n sì rẹ̀ sílẹ̀, òun kò sì kíyèsi i lára wọn.

22Ṣùgbọ́n ẹran-ara rẹ̀ ni yóò rí

ìrora. Ọkàn rẹ̀ ni yóò sì máa ní ìbìnújẹ́ nínú rẹ̀.”

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 14:1-22

1“ከሴት የተወለደ ሰው፣

ዘመኑ ዐጭርና በመከራ የተሞላ ነው፤

2እንደ አበባ ይፈካል፤ ይረግፋልም፤

እንደ ጥላ ይፈጥናል፤ አይጸናምም።

3እንደዚህ ባለ ሰው ላይ ዐይንህን ታሳርፋለህን?

ለፍርድስ በፊትህ ታቀርበዋለህን?14፥3 ሰብዓ ሊቃናት፣ ቩልጌትና ሱርስት እንዲሁ ሲሆን ዕብራይስጡ ግን ታቀርበኛለህን? ይላል

4ከርኩስ ነገር ውስጥ ንጹሕን ማን ሊያወጣ ይችላል?

አንድ እንኳ የሚችል የለም!

5የሰው ዕድሜ አስቀድሞ የተወሰነ ነው፤

የወራቱንም ብዛት ወስነህ አስቀምጠሃል፤

ሊያልፈው የማይችለውንም ገደብ አኖርህለት።

6እንግዲህ ዘመኑን እንደ ምንደኛ እስኪፈጽም ድረስ፣

ፊትህን ከእርሱ መልስ፤ ተወው።

7“ዛፍ እንኳ ቢቈረጥ፣

እንደ ገና ሊያቈጠቍጥ፣

አዳዲስ ቅርንጫፍም ሊያበቅል ተስፋ አለው።

8ሥሩ በምድር ውስጥ ቢያረጅ፣

ጕቶው በመሬት ውስጥ ቢበሰብስም፣

9የውሃ ሽታ ባገኘ ጊዜ ያቈጠቍጣል፤

እንደ ተተከለም ችግኝ ቅርንጫፍ ያወጣል።

10ሰው ግን ይሞታል፤ ክንዱንም ይንተራሳል፤

ነፍሱም ትወጣለች፤ ከእንግዲህስ የት ይገኛል?

11ውሃ ከባሕር ውስጥ እንደሚያልቅ፣

የወንዝ ውሃም ጠፍቶ እንደሚደርቅ፣

12እንደዚሁም ሰው ይተኛል፤ ቀናም አይልም፤

ሰማይ እስከሚያልፍ ድረስ አይነቃም፤

ከእንቅልፉም አይነሣም።

13“ምነው መቃብር14፥13 በዕብራይስጥ ሲኦል ማለት ነው። ውስጥ በሰወርኸኝ!

ቍጣህም እስከሚያልፍ በሸሸግኸኝ!

ምነው ቀጠሮ ሰጥተህ፣

ከዚያ በኋላ ባስታወስኸኝ!

14ሰው ከሞተ በኋላ ተመልሶ በሕይወት ይኖራል?

እድሳቴ14፥14 ወይም መፈታቴ እስከሚመጣ ድረስ፣

ተጋድሎ የሞላበትን ዘመኔን ሁሉ እታገሣለሁ።

15ትጠራኛለህ፤ እኔም እመልስልሃለሁ፤

የእጅህንም ሥራ ትናፍቃለህ።

16በዚያን ጊዜ በርግጥ ርምጃዬን ትከታተላለህ፤

ነገር ግን ኀጢአቴን አትቈጣጠርም።

17መተላለፌ በከረጢት ይቋጠራል፤

ኀጢአቴንም ትሸፍናለህ።

18“ተራራ እንደሚሸረሸርና እንደሚወድቅ፣

ዐለትም ከስፍራው እንደሚወገድ፣

19ውሃ ድንጋይን እንደሚቦረቡር፣

ጐርፍም ዐፈርን ዐጥቦ እንደሚወስድ፣

አንተም የሰውን ተስፋ ታጠፋለህ።

20አንድ ጊዜ ፈጽመህ ትበረታለህ፤ እርሱም ያልፋል፤

ገጽታውን ትቀይራለህ፤ ትሸኘዋለህም።

21ልጆቹ ቢከበሩ አያውቅም፤

ቢዋረዱም አያይም።

22የገዛ አካሉ ሕመም ብቻ ይሰማዋል፤

ለራሱም ብቻ ያለቅሳል።”