Jobu 12 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 12:1-25

Ìdáhùn Jobu

1Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé:

2“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,

ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!

3Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin:

èmi kò kéré sí i yín:

àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

4“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,

tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn:

à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.

5Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà,

gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.

6Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;

àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,

àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

7“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,

àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.

8Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,

àwọn ẹja inú Òkun yóò sì sọ fún ọ.

9Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan

wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?

10Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,

Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.

11Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí

tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?

12Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,

àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.

13“Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára:

Òun ló ni ìmọ̀ àti òye.

14Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;

Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.

15Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;

Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.

16Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;

Ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.

17Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò,

A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.

18Ó tú ìdè ọba,

Ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.

19Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò,

Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.

20Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,

Ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.

21Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá,

Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.

22Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,

Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.

23Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;

Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.

24Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,

A sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.

25Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,

Òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.

Swedish Contemporary Bible

Job 12:1-25

Job svarar Sofar

1Job svarade:

2Ja, visst är ni kloka människor!

All visdom kommer att dö ut med er!

3Men jag har förstånd, likväl som ni.

Jag är inte sämre än ni.

Vem vet inte redan det som ni säger?

4Jag har blivit till åtlöje för mina vänner,

jag som bad Gud om hjälp och som Gud svarade,

jag, en rättfärdig och fläckfri man,

har gjorts till åtlöje.

5Den bekymmerslöse som föraktar den som har problem

kommer själv att snava.12:5 Versen är svårtolkad och kan ev. också översättas: Den bekymmerslöse föraktar dem som har problem och ser problemen som de snavandes öde.

6Rövare bor ostörda i sina tält,

de som trotsar Gud lever i trygghet,

de som har sin gud i sin hand.12:6 Grundtextens innebörd är osäker i versens sista del.

7Fråga boskapen,

den kan undervisa dig.

Fråga fåglarna under himlen,

de kan tala om det för dig.

8Eller tala till jorden,

så undervisar den dig,

eller till fiskarna i havet,

så kan de berätta för dig.

9Vem av dessa vet inte

att det är Herrens hand som gjort detta?

10För varje varelses liv är i Guds hand,

och så är också varje människas ande.

11Prövar inte örat orden,

liksom tungan prövar matens smak?

12Visst kommer visdom med åren

och förstånd av ett långt liv.

13Hos Gud finns visdom och kraft,

hos honom finns råd och förstånd.

14Vad han bryter ner kan inte byggas upp.

Den han fångar kan inte fritas.

15Han håller vattnen tillbaka

och det blir torka,

släpper han dem lösa

ödelägger de landet.

16Hos honom finns styrka och förnuft.

Både bedragaren och den bedragne måste böja sig för honom.

17Han för bort rådgivare barfota

och gör domare till dårar.

18Han tar av kungarnas bojor

och binder ett skynke kring deras höfter.

19Präster leder han bort barfota.

Han låter de mäktiga komma på fall.

20Han tystar de betroddas tal

och fråntar de gamla deras insikt.

21Han öser förakt över furstar

och avväpnar de starka.

22Han avslöjar mörkrets hemligheter

och för fram den djupa skuggan till ljuset.

23Han gör nationer starka

och bryter sedan ner dem.

Han gör nationer stora

för att sedan skingra dem.

24Han berövar jordens ledare förståndet

och låter dem irra omkring i väglös ödemark.

25De famlar i ett mörker utan ljus,

och han låter dem ragla som druckna.