Jobu 11 – YCB & NVI

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 11:1-20

Sofari fi ẹ̀sùn irọ́ pípa àti àìṣòótọ́ kan Jobu

1Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé:

2“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?

A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?

3Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?

Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?

4Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé,

‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’

5Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,

kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ;

6Kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ;

Nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti

gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

7“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?

Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?

8Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?

Ó jì ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀?

9Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,

ó sì ní ibú ju Òkun lọ.

10“Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà,

tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?

11Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn;

àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?

12Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n,

bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.

13“Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,

tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,

14Bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù,

tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ.

15Nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n,

àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù,

16Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ,

ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.

17Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,

bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.

18Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà;

àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.

19Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́,

àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.

20Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo;

gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n,

ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”

Nueva Versión Internacional

Job 11:1-20

Primer discurso de Zofar

1A esto respondió Zofar de Namat:

2«¿Quedará sin respuesta toda esta palabrería?

¿Resultará inocente este hablador?

3¿Todo ese discurso nos dejará callados?

¿Te burlarás sin que nadie te reprenda?

4Tú afirmas: “Mi postura es la correcta;

soy puro a los ojos de Dios”.

5¡Cómo me gustaría que Dios interviniera

y abriera sus labios contra ti

6para mostrarte los secretos de la sabiduría,

pues esta tiene dos lados!11:6 esta tiene dos lados. Frase de difícil traducción.

Sabrías entonces que buena parte de tu pecado

Dios no lo ha tomado en cuenta.

7»¿Puedes adentrarte en los misterios de Dios

o alcanzar la perfección11:7 alcanzar la perfección. Alt. llegar hasta los límites. del Todopoderoso?

8Son más altos que los cielos;

¿qué puedes hacer?

Son más profundos que el abismo;11:8 abismo. Lit. Seol.

¿qué puedes saber?

9Son más extensos que toda la tierra;

¡son más anchos que todo el mar!

10»Si viene y te pone en un calabozo,

y luego te llama a cuentas,

¿quién lo hará desistir?

11Bien conoce Dios a la gente sin escrúpulos;

cuando percibe el mal, no lo pasa por alto.

12¡El necio llegará a ser sabio

cuando de un asno salvaje nazca un hombre!11:12 cuando … hombre. Alt. cuando los asnos salvajes nazcan domesticados.

13»Pero si le entregas tu corazón

y hacia él extiendes las manos,

14si te apartas del pecado que has cometido

y en tu morada no das cabida al mal,

15entonces podrás llevar la frente en alto

y mantenerte firme y libre de temor.

16Ciertamente olvidarás tus pesares

o los recordarás como el agua que pasó.

17Tu vida será más radiante que el sol de mediodía

y la oscuridad será como el amanecer.

18Vivirás tranquilo, porque hay esperanza;

estarás protegido11:18 estarás protegido. Alt. mirarás en torno tuyo (TM). y dormirás confiado.

19Descansarás sin temer a nadie

y muchos querrán ganarse tu favor.

20Pero los ojos de los malvados se apagarán;

no tendrán escapatoria.

¡Su esperanza es exhalar el último suspiro!».