Jobu 11 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 11:1-20

Sofari fi ẹ̀sùn irọ́ pípa àti àìṣòótọ́ kan Jobu

1Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé:

2“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?

A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?

3Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?

Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?

4Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé,

‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’

5Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,

kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ;

6Kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ;

Nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti

gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

7“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?

Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?

8Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?

Ó jì ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀?

9Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,

ó sì ní ibú ju Òkun lọ.

10“Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà,

tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?

11Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn;

àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?

12Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n,

bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.

13“Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,

tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,

14Bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù,

tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ.

15Nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n,

àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù,

16Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ,

ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.

17Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,

bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.

18Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà;

àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.

19Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́,

àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.

20Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo;

gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n,

ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”

Nouă Traducere În Limba Română

Iov 11:1-20

Primul discurs al lui Țofar

1Atunci Țofar naamatitul a răspuns și a zis:

2„Să rămână tot acest potop de cuvinte fără răspuns

și toate aceste vorbe multe să fie o dovadă a dreptății?

3Crezi că flecăreala ta va închide gura altora

și că‑ți vei bate joc de alții fără să te mustre nimeni?

4Tu zici: «Învățătura mea este curată

și sunt fără pată în ochii Tăi!»

5Însă cine n‑ar da ca Dumnezeu să vorbească,

să‑Și deschidă gura împotriva ta

6și să‑ți arate tainele înțelepciunii!?

Căci înțelepciunea are două fețe.

Atunci ai ști că Dumnezeu ți‑a iertat câte ceva din nelegiuirea ta.

7Poți tu să descoperi misterul lui Dumnezeu?

Poți tu să descoperi limita Celui Atotputernic?

8Ea este cât înălțimile cerurilor – ce poți face?

Ea este mai adâncă decât Locuința Morților – ce poți ști?

9Întinderea lor este mai lungă decât pământul

și mai largă decât marea.

10Dacă El trece și întemnițează

și cheamă la judecată, cine‑L poate opri?

11Căci El îi cunoaște pe oamenii înșelători,

iar când vede nelegiuirea, oare nu va lua seamă?

12Dar omul nătâng va deveni înțelept,

când se va naște om mânzul măgarului sălbatic.

13Dacă îți vei îndrepta inima

și îți vei ridica mâinile spre El,

14dacă vei înlătura nelegiuirea din mâna ta

și nu vei lăsa nedreptatea să locuiască în corturile tale,

15atunci îți vei putea ridica fața fără pată,

vei fi tare și nu te vei teme.

16Îți vei uita necazul

și‑ți vei aminti de el ca de apele care au trecut.

17Viața va fi mai strălucitoare ca amiaza;

deși este întuneric, acesta va fi ca dimineața.

18Vei fi încrezător pentru că va fi speranță,

vei fi păzit și te vei odihni în siguranță.

19Te vei culca și nimeni nu te va mai înspăimânta;

mulți vor căuta bunăvoința ta.

20Dar ochii celor răi se vor închide,

orice cale de scăpare va fi pierdută pentru ei

și speranța lor este să‑și dea ultima suflare.“