Jobu 10 – YCB & NIV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 10:1-22

Àròyé Jobu tẹ̀síwájú

1“Agara ìwà ayé mi dá mi tán,

èmi yóò tú àròyé mi sókè lọ́dọ̀ mi,

èmi yóò máa sọ̀rọ̀ nínú kíkorò ìbìnújẹ́ ọkàn mi.

2Èmi yóò wí fún Ọlọ́run pé: má ṣe dá mi lẹ́bi;

fihàn mí nítorí ìdí ohun tí ìwọ fi ń bá mi jà.

3Ó ha tọ́ tí ìwọ ìbá fi máa ni mí lára,

tí ìwọ ìbá fi máa gan iṣẹ́ ọwọ́ rẹ,

tí ìwọ yóò fi máa tàn ìmọ́lẹ̀ sí ìmọ̀ ènìyàn búburú.

4Ojú rẹ kì ha ṣe ojú ènìyàn bí?

Tàbí ìwọ a máa ríran bí ènìyàn ti í ríran?

5Ọjọ́ rẹ ha dàbí ọjọ́ ènìyàn,

ọdún rẹ ha dàbí ọjọ́ ènìyàn?

6Tí ìwọ fi ń béèrè àìṣedéédéé mi,

tí ìwọ sì fi wá ẹ̀ṣẹ̀ mi rí?

7Ìwọ mọ̀ pé èmi kì í ṣe oníwà búburú,

kò sì sí ẹni tí ó le gbà mí kúrò ní ọwọ́ rẹ?

8“Ọwọ́ rẹ ni ó mọ mi, tí ó sì da mi.

Síbẹ̀ ìwọ tún yípadà láti jẹ mí run.

9Èmi bẹ̀ ọ́ rántí pé ìwọ ti mọ mí bí amọ̀;

ìwọ yóò ha sì tún mú mi padà lọ sínú erùpẹ̀?

10Ìwọ kò ha ti tú mí dà jáde bí i wàrà,

ìwọ kò sì mú mí dìpọ̀ bí i wàràǹkàṣì?

11Ìwọ sá ti fi àwọ̀ ẹran-ara wọ̀ mí,

ìwọ sì fi egungun àti iṣan ṣọgbà yí mi ká.

12Ìwọ ti fún mi ní ẹ̀mí àti ojúrere,

ìbẹ̀wò rẹ sì pa ọkàn mi mọ́.

13“Nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ sì ti fi pamọ́ nínú rẹ;

èmi mọ̀ pé, èyí ń bẹ ní ọkàn rẹ.

14Bí mo bá ṣẹ̀, nígbà náà ni ìwọ yóò máa ṣọ́ mi

ìwọ kì yóò sì dárí àìṣedéédéé mi jì.

15Bí mo bá ṣe ẹni búburú, ègbé ni fún mi!

Bí mo bá sì ṣe ẹni rere,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì le gbe orí mi sókè.

Èmi dààmú, mo si wo ìpọ́njú mi.

16Bí mo bá gbé orí mi ga. Ìwọ ń dẹ mí kiri bi i kìnnìún;

àti pẹ̀lú, ìwọ a sì fi ara rẹ hàn fún mi ní ìyànjú.

17Ìwọ sì tún mun àwọn ẹlẹ́rìí rẹ dìde sí mi

di ọ̀tún, Ìwọ sì sọ ìrunú rẹ di púpọ̀ sí mi;

Àwọn ogun rẹ si dìde sinmi bi igbe omi Òkun.

18“Nítorí kí ni ìwọ ṣe mú mi jáde láti inú wá?

Háà! Èmi ìbá kúkú ti kú, ojúkójú kì bá tí rí mi.

19Tí kò bá le jẹ́ pé èmi wà láààyè,

À bá ti gbé mi láti inú lọ isà òkú.

20Ọjọ́ mi kò ha kúrú bí? Rárá!

Dáwọ́ dúró, kí ó sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ mi.

Nítorí kí èmi lè ni ayọ̀ ní ìṣẹ́jú kan.

21Kí èmi kí ó tó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà sẹ́yìn mọ́,

Àní si ilẹ̀ òkùnkùn àti òjìji ikú.

22Ilẹ̀ òkùnkùn bí òkùnkùn tìkára rẹ̀,

Àti ti òjìji ikú àti rúdurùdu,

Níbi tí ìmọ́lẹ̀ dàbí òkùnkùn.”

New International Version

Job 10:1-22

1“I loathe my very life;

therefore I will give free rein to my complaint

and speak out in the bitterness of my soul.

2I say to God: Do not declare me guilty,

but tell me what charges you have against me.

3Does it please you to oppress me,

to spurn the work of your hands,

while you smile on the plans of the wicked?

4Do you have eyes of flesh?

Do you see as a mortal sees?

5Are your days like those of a mortal

or your years like those of a strong man,

6that you must search out my faults

and probe after my sin—

7though you know that I am not guilty

and that no one can rescue me from your hand?

8“Your hands shaped me and made me.

Will you now turn and destroy me?

9Remember that you molded me like clay.

Will you now turn me to dust again?

10Did you not pour me out like milk

and curdle me like cheese,

11clothe me with skin and flesh

and knit me together with bones and sinews?

12You gave me life and showed me kindness,

and in your providence watched over my spirit.

13“But this is what you concealed in your heart,

and I know that this was in your mind:

14If I sinned, you would be watching me

and would not let my offense go unpunished.

15If I am guilty—woe to me!

Even if I am innocent, I cannot lift my head,

for I am full of shame

and drowned in10:15 Or and aware of my affliction.

16If I hold my head high, you stalk me like a lion

and again display your awesome power against me.

17You bring new witnesses against me

and increase your anger toward me;

your forces come against me wave upon wave.

18“Why then did you bring me out of the womb?

I wish I had died before any eye saw me.

19If only I had never come into being,

or had been carried straight from the womb to the grave!

20Are not my few days almost over?

Turn away from me so I can have a moment’s joy

21before I go to the place of no return,

to the land of gloom and utter darkness,

22to the land of deepest night,

of utter darkness and disorder,

where even the light is like darkness.”