Joṣua 19 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joṣua 19:1-51

Ìpín ti ẹ̀yà Simeoni

1Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda. 2Lára ìpín wọn ní:

Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada, 3Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu, 4Eltoladi, Betuli, Horma, 5Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa, 6Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.

7Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani: Ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn: 8Àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù).

Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé. 9A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.

Ìpín fún ẹ̀yà Sebuluni

10Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé:

Ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi. 11Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu. 12Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia. 13Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea. 14Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní Àfonífojì Ifita-Eli.

15Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.

16Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.

Ìpín fún ẹ̀yà Isakari

17Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé. 18Lára ilẹ̀ wọn ni èyí:

Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu, 19Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati, 20Rabiti, Kiṣioni, Ebesi, 21Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.

22Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani.

Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìn-dínlógún àti ìletò wọn.

23Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.

Ìpín fún ẹ̀yà Aṣeri

24Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé. 25Lára ilẹ̀ wọn ni èyí:

Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu, 26Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati. 27Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti Àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabuli ní apá òsì. 28Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá. 29Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun ní ilẹ̀ Aksibu, 30Uma, Afeki àti Rehobu.

Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.

31Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.

Ìpín fún ẹ̀yà Naftali

32Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé:

33Ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani. 34Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.

35Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti, 36Adama, Rama Hasori, 37Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri, 38Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi.

Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàn-dínlógún àti ìletò wọn.

39Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.

Ìpín fún ẹ̀yà Dani

40Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé. 41Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí:

Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi, 42Ṣaalabini, Aijaloni, Itila, 43Eloni, Timna, Ekroni, 44Elteke, Gibetoni, Baalati, 45Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni, 46Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.

47(Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).

48Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.

Ìpín fún ẹ̀yà Joṣua

49Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn 50Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún—Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.

51Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.