Joṣua 12 – Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn YCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Joṣua 12:1-24

Orúkọ àwọn ọba tí a ṣẹ́gun

112.1-5: Nu 21.21-35; De 2.26–3.11.Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé Òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:

2Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni.

Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín Àfonífojì náà dé Odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.

3Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.

4Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.

5Ó ṣe àkóso ní orí Òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.

6Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.

7Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní Àfonífojì Lebanoni sí Òkè Halaki, èyí tí O lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn: 8ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi):

9Ọba Jeriko ọ̀kan

Ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli) ọ̀kan

10Ọba Jerusalẹmu ọ̀kan

ọba Hebroni ọ̀kan

11Ọba Jarmatu ọ̀kan

ọba Lakiṣi ọ̀kan

12Ọba Egloni ọ̀kan

ọba Geseri ọ̀kan

13Ọba Debiri ọ̀kan

ọba Gederi ọ̀kan

14Ọba Horma ọ̀kan

ọba Aradi ọ̀kan

15Ọba Libina ọ̀kan

ọba Adullamu ọ̀kan

16Ọba Makkeda ọ̀kan

ọba Beteli ọ̀kan

17Ọba Tapua ọ̀kan

ọba Heferi ọ̀kan

18Ọba Afeki ọ̀kan

ọba Laṣaroni ọ̀kan

19Ọba Madoni ọ̀kan

ọba Hasori ọ̀kan

20Ọba Ṣimroni-Meroni ọ̀kan

ọba Akṣafu ọ̀kan

21Ọba Taanaki ọ̀kan

ọba Megido ọ̀kan

22Ọba Kedeṣi ọ̀kan

ọba Jokneamu ni Karmeli ọ̀kan

23Ọba Dori (ní Nafoti Dori) ọ̀kan

ọba Goyimu ní Gilgali ọ̀kan

24Ọba Tirsa ọ̀kan

gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.