Jeremiah 1 – YCB & NRT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 1:1-19

1Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini. 2Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda, 3Àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.

Ìpè Jeremiah

4Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,

51.5: Isa 49.1; Ga 1.15.Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n,

kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀.

Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.

6Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”

7Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.” 81.8: Isa 43.5; Ap 18.9-10.Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

9Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ 101.10: If 10.11.Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.

11Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé:

“Kí ni o rí Jeremiah?”

Mo sì dáhùn wí pé “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”

12Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”

13Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.

14Olúwa, sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà. 15Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí.

Àwọn ọba wọn yóò wá

gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé

Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo

àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn

ìlú Juda.

16Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi

nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀,

nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn

àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.

17“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn. 18Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. 19Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.

New Russian Translation

Иеремия 1:1-19

Пролог

1Слова Иеремии, сына Хелкии, одного из священников Анатота, что в земле Вениамина. 2Слово Господа было к нему в тринадцатом году1:2 В 627 г. до н. э. правления Иосии, сына Амона, царя Иудеи. 3Господь продолжал возвещать ему Свое слово во времена правления Иоакима, сына Иосии, царя Иудеи, до пятого месяца одиннадцатого года правления Цедекии1:3 В августе 586 г. до н. э., сына Иосии, царя Иудеи, когда жители Иерусалима были уведены в плен.

Призвание Иеремии

4И было ко мне слово Господне:

5– Прежде чем Я образовал тебя во чреве, Я уже знал1:5 Или: «избрал». тебя,

прежде чем ты вышел из утробы, Я избрал тебя;

Я назначил тебя пророком для народов.

6Я ответил:

– О Владыка Господь!1:6 Евр.: «Адонай ЙГВГ». Я не умею говорить, ведь я слишком молод.

7Но Господь сказал мне:

– Не говори: «Я еще молод». Ты пойдешь ко всем, к кому Я пошлю тебя, и будешь говорить все, что Я повелю тебе. 8Не бойся их, потому что Я с тобой, и Я спасу тебя, – сказал Господь.

9Господь простер руку, коснулся моих уст и сказал мне:

– Вот, Я вложил слова Мои в твои уста. 10Смотри, сегодня Я поставлю тебя над народами и царствами, чтобы искоренять и ломать, губить и разрушать, строить и насаждать.

11И было ко мне слово Господне:

– Что ты видишь, Иеремия?

– Вижу ветку миндального1:11 Евр.: «шакед». дерева, – ответил я.

12– Верно разглядел, – сказал мне Господь, – ведь Я бодрствую1:12 На языке оригинала: «шокед», что близко по звучанию к слову «шакед» – «миндаль». над Моим словом, чтобы его исполнить.

13Вновь было ко мне слово Господне:

– Что ты видишь?

– Вижу кипящий котел – он движется с севера, – ответил я.

14– С севера хлынет беда на всех, кто живет в этой стране, – сказал мне Господь. – 15Ведь Я призываю все народы северных царств, – возвещает Господь. –

Они придут и поставят свои престолы

у ворот Иерусалима,

вокруг всех окружающих его стен,

у всех городов Иудеи.

16Я оглашу приговор им

за все их злодеяния: они оставили Меня,

и возжигали благовония чужим богам,

и поклонялись делам своих рук.

17Соберись! Встань и скажи им все, что Я тебе повелю. Не бойся их, не то Я сокрушу тебя перед ними. 18Сегодня Я сделал тебя укрепленным городом, железной колонной и бронзовой стеной, чтобы дать отпор всей этой земле – царям Иудеи, ее вельможам, священникам и народу этой страны. 19Они будут воевать против тебя, но не одолеют, потому что Я с тобой и спасу тебя, – возвещает Господь.