Isaiah 1 – YCB & NASV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 1:1-31

1Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.

Ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè kan

2Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀:

“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,

Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.

3Màlúù mọ olówó rẹ̀,

kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,

ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀,

òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”

4Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,

àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,

Ìran àwọn aṣebi,

àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!

Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀

wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli,

wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.

5Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?

Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?

Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,

gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.

6Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín

kò sí àlàáfíà rárá,

àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa

àti ojú egbò,

tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.

7Orílẹ̀-èdè yín dahoro,

a dáná sun àwọn ìlú yín,

oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run

lójú ara yín náà,

ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí

àwọn àjèjì borí rẹ̀.

8Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀

gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,

gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí,

àti bí ìlú tí a dó tì.

9Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun

bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà,

a ò bá ti rí bí Sodomu,

a ò bá sì ti dàbí Gomorra.

10Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu,

tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,

ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!

11“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín

kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.

“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun

ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,

Èmi kò ní inú dídùn

nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn

àti ti òbúkọ.

12Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,

ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín,

Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?

13Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́!

Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,

oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ,

Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.

14Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn,

ni ọkàn mi kórìíra.

Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,

Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.

15Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà,

Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,

kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,

Èmi kò ni tẹ́tí sí i.

“Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.

16“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.

Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!

Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,

17kọ́ láti ṣe rere!

Wá ìdájọ́ òtítọ́,

tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.

Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

gbà ẹjọ́ opó rò.

18“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,”

ni Olúwa wí.

“Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn,

wọn ó sì funfun bí i yìnyín,

bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀,

wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.

19Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀,

ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.

20Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀,

idà ni a ó fi pa yín run.”

Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.

21Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè!

Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí,

òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí,

ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!

22Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,

ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.

23Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,

akẹgbẹ́ àwọn olè,

gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀

wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.

Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,

ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.

24Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé:

“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi

n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.

25Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,

èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,

n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.

26Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,

àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.

Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”

27A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà,

àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.

28Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun.

Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.

29“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́

èyí tí ẹ ní inú dídùn sí,

a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí

tí ẹ ti yàn fúnrayín.

30Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ,

bí ọgbà tí kò ní omi.

31Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná,

iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,

àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,

láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 1:1-31

1በይሁዳ ነገሥታት በዖዝያን፣ በኢዮአታም፣ በአካዝና በሕዝቅያስ ዘመን፣ የአሞጽ ልጅ ኢሳይያስ ስለ ይሁዳና ስለ ኢየሩሳሌም ያየው ራእይ፤

እንቢተኛ ሕዝብ

2ሰማያት ሆይ፤ ስሙ! ምድር ሆይ፤ አድምጪ!

እግዚአብሔር እንዲህ ሲል ተናግሯልና፤

“ልጆች ወለድሁ፣ አሳደግኋቸውም፤

እነርሱ ግን ዐመፁብኝ።

3በሬ ጌታውን፣

አህያ የባለቤቱን ጋጥ ያውቃል፤

እስራኤል ግን አላወቀም፤

ሕዝቤም አላስተዋለም።”

4እናንተ ኀጢአተኛ ሕዝብ፣

በደል የሞላበት ወገን፣

የክፉ አድራጊ ዘር፣

ምግባረ ብልሹ ልጆች ወዮላችሁ!

እግዚአብሔርን ትተዋል፤

የእስራኤልን ቅዱስ አቃልለዋል፤

ጀርባቸውንም በእርሱ ላይ አዙረዋል።

5ለምን ዳግመኛ ትመታላችሁ?

ለምንስ በዐመፅ ትጸናላችሁ?

ራሳችሁ በሙሉ ታምሟል፤

ልባችሁ ሁሉ ታውኳል።

6ከእግር ጥፍራችሁ እስከ ራስ ጠጕራችሁ

ጤና የላችሁም፤

ቍስልና ዕባጭ እንዲሁም እዥ ብቻ ነው፤

አልታጠበም፤ አልታሰረም፤

በዘይትም አልለዘበም።

7አገራችሁ ባድማ፣

ከተሞቻችሁ በእሳት የተቃጠሉ ይሆናሉ፤

ዐይናችሁ እያየ፣

መሬታችሁ በባዕድ ይነጠቃል፤

ጠፍም ይሆናል።

8የጽዮን ሴት ልጅ

በወይን አትክልት ውስጥ እንዳለ ዳስ፣

በዱባ ተክል ወስጥ እንደሚገኝ ጐጆ፣

እንደ ተከበበም ከተማ ተተወች።

9የሰራዊት ጌታ እግዚአብሔር

ዘርን ባያስቀርልን ኖሮ፣

እንደ ሰዶም በሆን፣

ገሞራንም በመሰልን ነበር።

10እናንተ የሰዶም ገዦች፤

የእግዚአብሔርን ቃል ስሙ፤

እናንተ የገሞራ ሰዎች፤

የእግዚአብሔርን ሕግ አድምጡ።

11“የመሥዋዕታችሁ ብዛት

ለእኔ ምኔ ነው?” ይላል እግዚአብሔር

“የሚቃጠለውን የአውራ በግና

የሠቡ እንስሳትን ሥብ ጠግቤአለሁ፤

በበሬ፣ በበግ ጠቦትና በፍየል ደም ደስ

አልሰኝም።

12በፊቴ ለመቅረብ ስትመጡ፣

ይህን ሁሉ እንድታመጡ፣

የመቅደሴን ደጅ እንድትረግጡ ማን ጠየቃችሁ?

13ከንቱውን መባ አታቅርቡ፤

ዕጣናችሁን እጸየፋለሁ፤

የወር መባቻ በዓላችሁን፣

ሰንበቶቻችሁን፣ ጉባኤያችሁንና

በክፋት የተሞላውን ስብሰባችሁን መታገሥ

አልቻልሁም።

14የወር መባቻችሁንና የተደነገጉ በዓሎቻችሁን

ነፍሴ ጠልታለች፤

ሸክም ሆነውብኛል፤

መታገሥም አልቻልሁም።

15እጆቻቸሁን ለጸሎት ወደ እኔ ስትዘረጉ፣

ዐይኖቼን ከእናንተ እሰውራለሁ፤

አብዝታችሁ ብትጸልዩም እንኳ አልሰማችሁም፤

እጆቻችሁ በደም ተበክለዋል፤

16ታጠቡ፤ ራሳችሁንም አንጹ፤

ክፉ ሥራችሁን ከፊቴ አርቁ፤

ክፉ ማድረጋችሁን ተዉ፤

17መልካም ማድረግን ተማሩ፤

ፍትሕን እሹ፣

የተገፉትን አጽናኑ1፥17 ወይም፣ ጨቋኙን ገሥጹ ማለት ነው።

አባት ለሌላቸው ቁሙላቸው፤

ለመበለቶችም ተሟገቱ።

18“ኑና እንዋቀሥ”

ይላል እግዚአብሔር

“ኀጢአታችሁ እንደ ዐለላ ቢቀላ፣

እንደ በረዶ ይነጣል፤

እንደ ደም ቢቀላም፣

እንደ ባዘቶ ነጭ ይሆናል።

19እሺ ብትሉ፣ ብትታዘዙም

የምድርን በረከት ትበላላችሁ፤

20እንቢ ብላችሁ ብታምፁ ግን

ሰይፍ ይበላችኋል።”

የእግዚአብሔር አፍ ይህን ተናግሯልና።

21ታማኝ የነበረችው ከተማ

እንዴት አመንዝራ እንደ ሆነች ተመልከቱ፤

ቀድሞ ፍትሕ የሞላባት፣

ጽድቅ የሰፈነባት ነበረች፤

አሁን ግን የነፍሰ ገዳዮች ማደሪያ ሆነች

22ብርሽ ዝጓል፣

ምርጥ የወይን ጠጅሽ ውሃ ገባው፤

23ገዥዎችሽ ዐመፀኞችና

የሌባ ግብረ ዐበሮች ናቸው፤

ሁሉም ጕቦን ይወድዳሉ፤

እጅ መንሻንም በብርቱ ይፈልጋሉ፤

አባት ለሌላቸው አይቆሙም፤

የመበለቶችንም አቤቱታ አይሰሙም።

24ስለዚህ ጌታ፣ የሰራዊት ጌታ እግዚአብሔር

የእስራኤል ኀያል እንዲህ ይላል፤

“በባላንጣዎቼ ላይ ቍጣዬን እገልጣለሁ፤

ጠላቶቼንም እበቀላለሁ።

25እጄን በአንቺ ላይ አነሣለሁ፤

ዝገትሽን ፈጽሜ አጠራለሁ፤

ጕድፍሽንም ሁሉ አስወግዳለሁ።

26ፈራጆችሽን እንደ ጥንቱ፣

አማካሪዎችሽንም እንደ ቀድሞው እመልሳለሁ፤

ከዚያም የጽድቅ መዲና፣

የታመነች ከተማ

ተብለሽ ትጠሪያለሽ።”

27ጽዮን በፍትሕ፣

በንስሓ የሚመለሱ ነዋሪዎቿም በጽድቅ ይዋጃሉ።

28ዐመፀኞችና ኀጢአተኞች ግን በአንድነት ይደቅቃሉ፤

እግዚአብሔርንም የሚተዉ ይጠፋሉ።

29“ደስ በተሰኛችሁባቸው የአድባር ዛፎች

ታፍራላችሁ፤

በመረጣችኋቸውም የአትክልት ቦታዎች

ትዋረዳላችሁ።

30ቅጠሉ እንደ ጠወለገ ወርካ፣

ውሃም እንደሌለው የአትክልት ቦታ ትሆናላችሁ።

31ብርቱ ሰው እንደ ገለባ፣

ሥራውም እንደ ብልጭታ ይሆናል፤

ሁለቱም አብረው ይቃጠላሉ፤

እሳቱንም የሚያጠፋው የለም።”