Àìronúpìwàdà Israẹli
1“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a padà sọ́dọ̀ Olúwa
ó ti fà wá ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ
ṣùgbọ́n yóò mú wa láradá
Ó ti pa wá lára
ṣùgbọ́n yóò dí ojú ọgbẹ́ wa.
2Lẹ́yìn ọjọ́ méjì, yóò sọ wá jí
ní ọjọ́ kẹta yóò mú wa padà bọ̀ sípò
kí a ba à le wá gbé níwájú rẹ̀
3Ẹ jẹ́ kí a mọ Olúwa
Ẹ jẹ́ kí a tẹ̀síwájú láti mọ̀ ọ́n.
Gẹ́gẹ́ bí oòrùn ṣe ń yọ,
Yóò jáde;
Yóò tọ̀ wá wá bí òjò
bí òjò àkọ́rọ̀ ti ń bomirin ilẹ̀.”
4“Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Efraimu?
Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Juda?
Ìfẹ́ rẹ dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀
bí ìrì ìdájí tí ó kọjá lọ kíákíá.
5Nítorí náà ni mo ṣe gé e yín sí wẹ́wẹ́ láti ọwọ́ àwọn wòlíì.
Mo pa yín pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ẹnu mi
Ìdájọ́ mi tàn bí i mọ̀nàmọ́ná lórí yín
66.6: Mt 9.13; 12.7.Nítorí àánú ni mo fẹ́, kì í ṣe ẹbọ;
àti ìmọ̀ Ọlọ́run ju ọrẹ ẹbọ sísun lọ.
7Bí i Adamu, wọ́n da májẹ̀mú
wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi níbẹ̀.
8Gileadi jẹ́ ìlú àwọn ènìyàn búburú
tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, a sí ti fi ẹ̀ṣẹ̀ bà á jẹ́.
9Bí adigunjalè ṣe ń ba ní bùba de àwọn ènìyàn
bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà, ń parapọ̀;
tí wọ́n sì ń pànìyàn lójú ọ̀nà tó lọ sí Ṣekemu,
tí wọ́n sì ń dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ni lójú.
10Mo ti rí ohun tó ba ni lẹ́rù
ní ilé Israẹli.
Níbẹ̀ Efraimu, fi ara rẹ̀ fún àgbèrè
Israẹli sì di aláìmọ́.
11“Àti fún ìwọ, Juda
A ti yan ọjọ́ ìkórè rẹ.
“Nígbà tí mo bá fẹ́ dá ohun ìní àwọn ènìyàn mi padà,
Israel Unrepentant
1“Come, let us return to the Lord.
He has torn us to pieces
but he will heal us;
he has injured us
but he will bind up our wounds.
2After two days he will revive us;
on the third day he will restore us,
that we may live in his presence.
3Let us acknowledge the Lord;
let us press on to acknowledge him.
As surely as the sun rises,
he will appear;
he will come to us like the winter rains,
like the spring rains that water the earth.”
4“What can I do with you, Ephraim?
What can I do with you, Judah?
Your love is like the morning mist,
like the early dew that disappears.
5Therefore I cut you in pieces with my prophets,
I killed you with the words of my mouth—
then my judgments go forth like the sun.6:5 The meaning of the Hebrew for this line is uncertain.
6For I desire mercy, not sacrifice,
and acknowledgment of God rather than burnt offerings.
7As at Adam,6:7 Or Like Adam; or Like human beings they have broken the covenant;
they were unfaithful to me there.
8Gilead is a city of evildoers,
stained with footprints of blood.
9As marauders lie in ambush for a victim,
so do bands of priests;
they murder on the road to Shechem,
carrying out their wicked schemes.
10I have seen a horrible thing in Israel:
There Ephraim is given to prostitution,
Israel is defiled.
11“Also for you, Judah,
a harvest is appointed.
“Whenever I would restore the fortunes of my people,