Heberu 1 – YCB & SNC

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Heberu 1:1-14

Ọmọ tí o ṣe pàtàkì fún àwọn Angẹli

1Ní ìgbà àtijọ́, Ọlọ́run bá àwọn baba ńlá wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì ní ọ̀pọ̀ ìgbà àti ní onírúurú ọ̀nà, 2ṣùgbọ́n ní ìgbà ìkẹyìn yìí Ọlọ́run ń bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi, ẹni tí ó fi ṣe ajogún ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá gbogbo ayé yìí àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀: 3Ọmọ tí í ṣe ìtànṣán ògo Ọlọ́run àti àwòrán òun tìkára rẹ̀, tí ó sì ń fi ọ̀rọ̀ agbára rẹ̀ mú ohun gbogbo dúró: Lẹ́yìn tí ó ti ṣe ìwẹ̀nù ẹ̀ṣẹ̀ wa tan, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọláńlá ní òkè. 4Nítorí náà, ó sì ti fi bẹ́ẹ̀ di ẹni tí ó ga ní ipò ju angẹli lọ, bí ó ti jogún orúkọ èyí tí ó tayọ̀ tiwọn.

51.5: Sm 2.7; 2Sa 7.14.Nítorí kò sí ọ̀kan nínú àwọn angẹli tí Ọlọ́run fi ìgbà kan sọ fún pé:

“Ìwọ ni ọmọ mi;

lónìí ni mo bí ọ”?

Àti pẹ̀lú pé;

“Èmi yóò jẹ́ baba fún un,

Òun yóò sì jẹ́ ọmọ mi”?

61.6: De 32.43; Sm 97.7.Àti pẹ̀lú, nígbà tí Ọlọ́run rán àkọ́bí rẹ̀ wá si ayé wa yìí. Ó pàṣẹ pé,

“Ẹ jẹ́ kí gbogbo àwọn angẹli Ọlọ́run foríbalẹ̀ fún un.”

71.7: Sm 104.4.Àti nípa ti àwọn angẹli, ó wí pé;

“Ẹni tí ó dá àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀mí,

àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”

81.8-9: Sm 45.6-7.Ṣùgbọ́n ó sọ nípa tí Ọmọ rẹ̀ pé,

“Ìtẹ́ rẹ, Ọlọ́run, láé àti láéláé ni,

ọ̀pá aládé òdodo ni ọ̀pá ìjọba rẹ.

9Ìwọ fẹ́ òdodo, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kórìíra iṣẹ́ búburú;

nítorí èyí ni Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ ṣe fi ààmì òróró ayọ̀ yàn ọ

tí ó gbé ọ ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”

10Ó tún sọ pé,

“Ní àtètèkọ́ṣe, ìwọ Olúwa, ìwọ fi ìdí ayé sọlẹ̀,

àwọn ọ̀run sì jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ.

11Wọn yóò ṣègbé, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà síbẹ̀

gbogbo wọn ni yóò di àkísà bí ẹ̀wù.

12Ní kíká ni ìwọ yóò ká wọn bí aṣọ,

bí ìpààrọ̀ aṣọ ni a ó sì pààrọ̀ wọn.

Ṣùgbọ́n ìwọ fúnrarẹ̀ kì yóò yípadà

àti pé ọdún rẹ kì yóò ní òpin.”

131.13: Sm 110.1.Èwo nínú àwọn angẹli ní a gbọ́ pé Ọlọ́run fi ìgbà kan wí fún pé,

“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi

títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ

di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ”?

14Kì í ha á ṣe ẹ̀mí tí ń jíṣẹ́ ni àwọn angẹli í ṣe bí; tí a rán lọ síta láti máa ṣiṣẹ́ fún àwọn tí yóò jogún ìgbàlà?

Slovo na cestu

Židům 1:1-14

Ježíš Kristus je rovný Otci

1Bůh mluvil odedávna k otcům mnoha různými způsoby prostřednictvím proroků a odhaloval jim postupně své plány. 2V tomto posledním čase k nám promluvil ve svém Synu.

Boží Syn je podivuhodná bytost. Bůh mu vše dal a skrze něho stvořil svět a vše, co je v něm. 3On vyzařuje Boží lásku. Každý jeho čin a každé jeho slovo dosvědčuje, že je Bůh. Řídí vesmír podmanivou silou svého rozkazu. Zemřel, aby očistil naše svědomí od všech hříchů, vstal z mrtvých a pak se posadil na čestné místo u Boha.

Boží Syn je vyšší než andělé

4Boží Syn převyšuje i Boží posly – anděly. Jeho jméno to dokazuje. 5Vždyť Bůh nikdy neřekl andělu:

„Ty jsi můj Syn,

kterého jsem dnes zplodil.“

Ani:

„Budu mu otcem a on mi bude synem.“

6Ale když uvádí svého prvorozeného Syna na zem, říká:

„Ať se mu klanějí všichni Boží andělé.“

7Bůh mluví o svých andělích jako o vanutí větru a plamenech ohně, 8ale o svém Synu říká:

„Ty budeš, Bože, vládnout navzdory všem změnám

a tvoje vláda bude spravedlivá.

9Miluješ spravedlnost a nenávidíš svévoli.

Proto ti Bůh učinil radost a vyvýšil tě nad tvé druhy.“

10„Ty jsi, Pane, na počátku učinil zemi

a nebesa jsou dílo tvých rukou.

11Nebesa se rozplynou, ale ty zůstaneš.

12Obnosí se jako plášť a jednou je odložíš a vyměníš.

Ty však nezestárneš a nezahyneš.“

13Bůh nikdy nevyzval žádného anděla,

aby se posadil na čestné místo nedaleko něho,

dokud mu nepodrobí všechny nepřátele.

14Andělé jsou jen duchovní poslové, kteří jsou vysíláni, aby pečovali o ty, kterým se má dostat spásy jako dědictví.